Ìtòlẹ́sẹẹsẹ fún Ọ̀sẹ̀ April 6
Ọ̀SẸ̀ TÓ BẸ̀RẸ̀ NÍ APRIL 6
Orin 124 àti Àdúrà
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ:
cl orí 22 ìpínrọ̀ 18 sí 22, àti àpótí tó wà lójú ìwé 228 (30 min.)
Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run:
Bíbélì kíkà: 1 Sámúẹ́lì 16-18 (8 min.)
No. 1: 1 Sámúẹ́lì 18:17-24 (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
No. 2: Ṣé Ọlọ́run Ló Lẹ́bi Ìyà Tó Ń Jẹ Aráyé?—igw ojú ìwé 14 ìpínrọ̀ 1 sí 4 (5 min.)
No. 3: Ìdí Tí Àwọn Aláṣẹ Tó Mọ Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà Dáadáa Fi Máa Ń Yìn Wá—Róòmù 13:3 (5 min.)
Ìpàdé Iṣẹ́ Ìsìn:
ẸṢIN Ọ̀RỌ̀ OṢÙ YÌÍ: “Gbára Dì fún Iṣẹ́ Rere Gbogbo.”—Títù 3:1.
10 min: Múra Sílẹ̀ Láti Lo Àwọn Ìwé Ìròyìn Lóṣù April. Ìjíròrò. Kọ́kọ́ fi àwọn àbá tó wà lójú ìwé yìí ṣe àṣefihàn bí a ṣe lè fi àwọn ìwé ìròyìn náà lọni. Lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ náà láti ìbẹ̀rẹ̀ dópin.
10 min: Báwo La Ṣe Ṣe Sí? Ìjíròrò. Ní kí àwọn ará sọ bí wọ́n ṣe jàǹfààní nígbà tí wọ́n lo àwọn àbá tó wà nínú àpilẹ̀kọ náà, “Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I—Wá Àwọn Tí Wàá Máa Fún Ní Ìwé Ìròyìn Déédéé.” Ní kí wọ́n sọ àwọn ìrírí tó gbádùn mọ́ni tí wọ́n ní.
10 min: Ohun tó ń fẹ́ àbójútó nínú ìjọ.
Orín 106 àti Àdúrà