Ìtòlẹ́sẹẹsẹ fún Ọ̀sẹ̀ October 5
Ọ̀SẸ̀ TÓ BẸ̀RẸ̀ NÍ OCTOBER 5
Orin 13 àti Àdúrà
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ:
cl orí 31 ìpínrọ̀ 13 sí 20 (30 min.)
Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run:
Bíbélì kíkà: 1 Kíróníkà 1-4 (8 min.)
No. 1: 1 Kíróníkà 1:28-42 (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
No. 2: Báwo Ni Róòmù 8:26, 27 Ṣe Mú Kó Dá Wa Lójú Pé Ọlọ́run Nífẹ̀ẹ́ Wa? (5 min.)
No. 3: Ǹjẹ́ Èèyàn Lè Lóye Bíbélì? Báwo Ni A Ṣe Lè Lóyè Rẹ̀?—wp13 4/1 ojú ìwé 16 ìpínrọ̀ 1 sí 4 (5 min.)
Ìpàdé Iṣẹ́ Ìsìn:
ẸṢIN Ọ̀RỌ̀ OṢÙ YÌÍ: “Jẹ́rìí kúnnákúnná sí ìhìn rere.”—Ìṣe 20:24.
10 min: Fi Àwọn Ìwé Ìròyìn Lọni Lóṣù October. Ìjíròrò. Kọ́kọ́ fi àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tó wà lójú ìwé yìí ṣe àṣefihàn méjì nípa bí a ṣe lè fi àwọn ìwé ìròyìn náà lọni. Lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ náà láti ìbẹ̀rẹ̀ dópin.
10 min: Ohun tó ń fẹ́ àbójútó nínú ìjọ.
10 min: Báwo La Ṣe Ṣe Sí? Ìjíròrò. Ní kí àwọn ará sọ bí wọ́n ṣe jàǹfààní nígbà tí wọ́n lo àwọn àbá tó wà nínú àpilẹ̀kọ náà, “Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I—Bó O Ṣe Lè Wàásù ní Ìpínlẹ̀ Tí Wọ́n Ti Ń Ṣiṣẹ́ Ajé.” Ní kí àwọn ará sọ àwọn ìrírí tó gbádùn mọ́ni tí wọ́n ní.
Orin 98 àti Àdúrà