Ìtòlẹ́sẹẹsẹ fún Ọ̀sẹ̀ November 2
Ọ̀SẸ̀ TÓ BẸ̀RẸ̀ NÍ NOVEMBER 2
Orin 52 àti Àdúrà
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ:
ia orí 1 ìpínrọ̀ 14 sí 27, àtúnyẹ̀wò tó wà lójú ìwé 16 (30 min.)
Ilé Ẹ̀kọ́ Ìjọba Ọlọ́run:
Bíbélì kíkà: 1 Kíróníkà 16-20 (8 min.)
No. 1: 1 Kíróníkà 17:15-27 (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
No. 2: Ìrètí Wo Ló Wà fún Àwọn Tó Ti Kú?—wp13 10/1 ojú ìwé 16 ìpínrọ̀ 1 àti 2 (5 min.)
No. 3: Àwọn Ọ̀nà Tá A Lè Gbà “Máa Fi Ire Ṣẹ́gun Ibi”—Róòmù 12:21 (5 min.)
Ìpàdé Iṣẹ́ Ìsìn:
Ẹṣin Ọ̀rọ̀ Oṣù Yìí: ‘Ẹ ta gbòǹgbò kí ẹ sì fẹsẹ̀ múlẹ̀ nínú ìgbàgbọ́.’—Kól. 2:6, 7.
10 min: Fi Àwọn Ìwé Ìròyìn Lọni Lóṣù November. Ìjíròrò. Kọ́kọ́ fi àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ tó wà lójú ìwé yìí ṣe àṣefihàn méjì nípa bí a ṣe lè fi àwọn ìwé ìròyìn náà lọni. Lẹ́yìn náà, ẹ jíròrò àwọn ọ̀nà ìgbọ́rọ̀kalẹ̀ náà láti ìbẹ̀rẹ̀ dópin.
10 min: Ohun tó ń fẹ́ àbójútó nínú ìjọ.
10 min: Báwo La Ṣe Ṣe Sí? Ìjíròrò. Ní kí àwọn ará sọ bí wọ́n ṣe jàǹfààní nígbà tí wọ́n lo àwọn àbá tó wà nínú àpilẹ̀kọ náà, “Mú Kí Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Sunwọ̀n Sí I—Bí O Ṣe Lè Kọ́ Àwọn Akẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Rẹ Láti Máa Dá Kẹ́kọ̀ọ́ Dáadáa.” Ní kí àwọn ará sọ àwọn ìrírí tó gbádùn mọ́ni tí wọ́n ní.
Orin 140 àti Àdúrà
Ìránnilétí: Ẹ jọ̀wọ́, ẹ kọ́kọ́ gbọ́ orin yìí lẹ́ẹ̀kan. Lẹ́yìn náà, kí àwọn ará kọ orin tuntun yìí.