Àwọn Ìtẹ̀jáde Tá A Tọ́ka sí Nínú Ìwé Ìpàdé Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni
JANUARY 16-22
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | AÍSÁYÀ 34-37
“Ọlọ́run San Hesekáyà Lẹ́san Torí Pé Ó Nígbàgbọ́”
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run
Ẹ Máa Wà Ní Mímọ́ Nínú Ìbẹ̀rù Ọlọ́run
‘Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́ Yóò Wà Níbẹ̀’
Jèhófà sọ tẹ́lẹ̀ pé àwọn èèyàn òun tó wà nígbèkùn ní Bábílónì yóò padà sí ìlú ìbílẹ̀ wọn. Àsọtẹ́lẹ̀ nípa bí wọ́n ṣe máa padà sí ìlú wọn yẹn fún wọn ní ìdánilójú kan, ó sọ pé: “Dájúdájú, òpópó kan yóò sì wá wà níbẹ̀, àní ọ̀nà kan; Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́ sì ni a ó máa pè é.” (Aísá. 35:8a) Àsọtẹ́lẹ̀ yìí fi hàn pé yàtọ̀ sí pé Jèhófà máa ṣe ọ̀nà àbáyọ fún àwọn Júù láti padà wálé, ó tún mú un dá wọn lójú pé òun yóò dáàbò bò wọ́n lójú ọ̀nà.
Ẹ Máa Wà Ní Mímọ́ Nínú Ìbẹ̀rù Ọlọ́run
“Aláìmọ́ Kì Yóò Gbà Á Kọjá”
Lọ́dún 537 ṣáájú Sànmánì Kristẹni, ohun pàtàkì kan wà tá à ń retí látọ̀dọ̀ àwọn Júù tó ń padà lọ sí ìlú wọn. Aísáyà 35:8b sọ nípa àwọn tí wọ́n yẹ láti máa rin “Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́” yẹn pé: “Aláìmọ́ kì yóò gbà á kọjá. Yóò sì wà fún ẹni tí ń rìn lójú ọ̀nà, òmùgọ̀ kankan kì yóò sì rìn káàkiri lórí rẹ̀.” Nígbà tó jẹ́ pé torí káwọn Júù lè mú ìjọsìn tòótọ́ padà bọ̀ sípò ni wọ́n fi padà sí Jerúsálẹ́mù, kò ní sáyè fáwọn onímọtara ẹni nìkan, àwọn tí kò bọ̀wọ̀ fún ohun mímọ́ tàbí àwọn tó ń ṣohun ẹlẹ́gbin. Wọ́n ní láti máa pa ìlànà Jèhófà nípa ìwà rere mọ́. Lónìí, àwọn tó bá fẹ́ rí ojú rere Ọlọ́run ní láti ṣe ohun kan náà. Wọ́n ní láti máa wà ní ‘mímọ́ nínú ìbẹ̀rù Ọlọ́run.’ (2 Kọ́r. 7:1) Àwọn ohun àìmọ́ wo ló wá yẹ ká yẹra fún?
Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Aísáyà—Apá Kejì
Ẹ̀kọ́ Tá A Rí Kọ́:
36:2, 3, 22. Bó tilẹ̀ jẹ́ pé wọ́n gbaṣẹ́ ìríjú lọ́wọ́ Ṣébínà, síbẹ̀ wọ́n jẹ́ kó máa ṣe akọ̀wé fún ẹni tí wọ́n fi rọ́pò rẹ̀ láàfin. (Aísáyà 22:15, 19) Tí wọ́n bá gba ẹrù iṣẹ́ lọ́wọ́ wa nínú ètò Jèhófà nítorí ìdí kan, ṣé kò yẹ ká máa sin Ọlọ́run nìṣó ní ipò yòówù tó bá fi wá sí?
JANUARY 23-29
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | AÍSÁYÀ 38-42
“Jèhófà Ń Fi Agbára fún Ẹni Tó Ti Rẹ̀”
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run
“Ọlọ́run Jẹ́ Ìfẹ́”
17 Nínú orin wíwúni lórí kan tí Hesekáyà fi dúpẹ́ lọ́wọ́ Jèhófà lẹ́yìn tó mú kó bọ́ nínú àìsàn gbẹ̀mígbẹ̀mí kan, ó sọ fún Jèhófà pé: “O ti ju gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ẹ̀yìn rẹ.” (Aísáyà 38:17) Ohun tí ibí yìí ń sọ ni pé Jèhófà mú ẹ̀ṣẹ̀ ẹnì kan tó ti ronú pìwà dà, ó sì jù ú sẹ́yìn Rẹ̀, níbi tí Òun ò ti ní rí i tàbí kó rántí rẹ̀ mọ́. Gẹ́gẹ́ bí ìwé kan ti wí, èrò tí ibí yìí gbé yọ ni pé: “O ti jẹ́ kí [ẹ̀ṣẹ̀ mi] dà bí èyí tí kò tilẹ̀ wáyé rí rárá.” Ǹjẹ́ èyí kò tuni nínú?