ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | ÌSÍKÍẸ́LÌ 6-10
Ṣé O Máa Wà Lára Àwọn Tá A Máa Sàmì Sí Láti Là Á Já?
Ìran ohun tí Ìsíkíẹ́lì rí kọ́kọ́ ṣẹlẹ̀ nígbà tí Jerúsálẹ́mù àtijọ́ pa run. Báwo ni ìran yẹn ṣe máa ṣẹ lóde òní?
Ọkùnrin tó ní ìwo yíǹkì akọ̀wé ṣàpẹẹrẹ Jésù Kristi
Àwọn ọkùnrin mẹ́fà tó ní àwọn ohun ìjà tó lè fọ́ nǹkan túútúú ṣàpẹẹrẹ àwọn ọmọ ogun ọ̀run, Kristi tó jẹ́ olórí wọn sì wà pẹ̀lú wọn
Lákòókò tí ìpọ́njú ńlá bá ń lọ lọ́wọ́, Jésù máa ṣe ìdájọ́ ogunlọ́gọ̀ ńlá náà, ó sì máa sàmì sí wọn pé wọ́n jẹ́ àgùntàn