ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb19 October ojú ìwé 5
  • Ìwà Mímọ́ àti Ọ̀wọ̀ Tó Jinlẹ̀ Máa Ń Yíni Lọ́kàn Pa Dà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìwà Mímọ́ àti Ọ̀wọ̀ Tó Jinlẹ̀ Máa Ń Yíni Lọ́kàn Pa Dà
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Bọ̀wọ̀ fún Ọkọ Tàbí Aya Rẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2011
  • Ẹ Jẹ́ Kí Ọlọ́run Ràn Yín Lọ́wọ́ Kí Ẹ Lè Jẹ́ Tọkọtaya Aláyọ̀
    Ìdílé Rẹ Lè Jẹ́ Aláyọ̀
  • Ẹ Jẹ́ Olóòótọ́ sí Ara Yín
    Ìdílé Rẹ Lè Jẹ́ Aláyọ̀
  • Bí Ẹ Ṣe Lè Jẹ́ Kí Àlàáfíà Jọba Láàárín Ẹ̀yin Àtàwọn Mọ̀lẹ́bí Yín
    Ìdílé Rẹ Lè Jẹ́ Aláyọ̀
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2019
mwb19 October ojú ìwé 5

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ìwà Mímọ́ àti Ọ̀wọ̀ Tó Jinlẹ̀ Máa Ń Yíni Lọ́kàn Pa Dà

Lọ́pọ̀ ìgbà, ìwà rere àwọn ìyàwó tó kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́ ló máa ń mú kí ọkọ wọn náà kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́. Àmọ́, èyí lè gba pé kí wọ́n fara da àtakò fún ọ̀pọ̀ ọdún. (1Pe 2:21-23; 3:1, 2) Tó bá jẹ́ pé ìwọ náà ń kojú irú àtakò bẹ́ẹ̀, má ṣe jáwọ́ nínú fífi ire ṣẹ́gun ibi. (Ro 12:21) Irú ìwà bẹ́ẹ̀ lè gbéṣẹ́ ju ọ̀rọ̀ ẹnu lọ, ó sì lè mú kí ọkọ rẹ yí pa dà kó sì wá kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́.

Má ṣe máa rin kinkin mọ́ èrò tìẹ, kàkà bẹ́ẹ̀ máa gba ti ẹnì kejì ẹ rò. (Flp 2:3, 4) Máa fìfẹ́ hàn sí i, kó o sì máa ṣe ojúṣe ẹ̀ nínú ilé tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀. Yàtọ̀ síyẹn, máa fetí sílẹ̀ dáadáa. (Jem 1:19) Máa ṣe sùúrù, kó o sì jẹ́ kí ẹnì kejì ẹ mọ̀ pé ìfẹ́ rẹ̀ ò kúrò lọ́kàn ẹ. Kódà, tẹ́nì kejì rẹ ò bá fi bẹ́ẹ̀ fìfẹ́ hàn sí ẹ tàbí tí ò bọ̀wọ̀ fún ẹ, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà ń rí gbogbo ohun tó ò ń kojú, ó sì mọyì bó o ṣe jẹ́ olóòótọ́.​—1Pe 2:19, 20.

WO FÍDÍÒ NÁÀ JÈHÓFÀ Ń FÚN WA LÓKUN KÁ LÈ GBÉ ẸRÙ WA, KÓ O SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Báwo ni nǹkan ṣe rí fún Grace Li nígbà tó ṣègbéyàwó?

  • Kí ló mú kó nífẹ̀ẹ́ ẹ̀kọ́ òtítọ́?

  • Àwọn ìṣòro wo ni Arábìnrin Li kojú lẹ́yìn tó ṣèrìbọmi?

  • Àdúrà wo ni Arábìnrin Li gbà nítorí ọkọ rẹ̀?

  • Àwọn ìbùkún wo ni Arábìnrin Li ti rí torí pé ó ń hùwà mímọ́, ó sì ní ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ fún ọkọ ẹ̀?

Àwòrán látinú fídíò ‘Jèhófà Ń Fún Wa Lókun Ká Lè Gbé Ẹrù Wa,’ tó jẹ́ ká rí bí Grace Li ṣe tẹ̀ síwájú. 1. Grace ń sunkún ní ẹ̀yìnkùlé ilé rẹ̀. 2. Arábìnrin kan ń kọ́ Grace Li lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. 3. Grace àtàwọn ọmọ rẹ̀ fi ṣọ́ọ̀bù tí wọ́n ti ń ta oúnjẹ sílẹ̀ kí wọ́n lè lọ sípàdé. 4. Grace àtàwọn mẹ́sàn-án nínú ìdílé rẹ̀ ní Gbọ̀ngàn Ìjọba.

Ìwà mímọ́ àti ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ máa ń yíni lọ́kàn pa dà!

Ó tún ṣe pàtàkì kí arábìnrin náà máa hùwà mímọ́, kó sì ní ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ kódà tí ọkọ ẹ̀ tó ti ṣèrìbọmi kò bá fọwọ́ pàtàkì mú nǹkan tẹ̀mí. Wo fídíò náà O Lè Fún Ẹnì Kejì Rẹ Níṣìírí “Láìsọ Ohunkóhun.”

Arábìnrin kan ń wo ọkọ rẹ̀ tí kò lọ sípàdé
    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́