May 18-24
JẸ́NẸ́SÍSÌ 40-41
Orin 8 àti Àdúrà
Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)
ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN
“Jèhófà Gba Jósẹ́fù Sílẹ̀”: (10 min.)
Jẹ 41:9-13—Fáráò gbọ́ nípa Jósẹ́fù (w15 2/1 14 ¶4-5)
Jẹ 41:16, 29-32—Jèhófà fi ìtumọ̀ àwọn àlá Fáráò han Jósẹ́fù (w15 2/1 14-15)
Jẹ 41:38-40—Jósẹ́fù di igbá kejì Fáráò Ọba Íjíbítì (w15 2/1 15 ¶2)
Máa Walẹ̀ Jìn Nínú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: (10 min.)
Jẹ 41:14—Kí nìdí tí Jósẹ́fù fi fá irun rẹ̀ kó tó lọ rí Fáráò? (w15 11/1 9 ¶1-3)
Jẹ 41:33—Kí la rí kọ́ nínú ọ̀nà tí Jósẹ́fù gbà bá Fáráò sọ̀rọ̀? (w09 11/15 28 ¶14)
Àwọn ìṣúra tẹ̀mí wo lo tún rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí nípa Jèhófà, iṣẹ́ ìwàásù tàbí àwọn nǹkan míì?
Bíbélì Kíkà: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Jẹ 40:1-23 (th ẹ̀kọ́ 2)
MÁA LO ARA RẸ LẸ́NU IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́—Fídíò: (5 min.) Ìjíròrò. Jẹ́ kí àwọn ará wo fídíò náà, lẹ́yìn náà béèrè àwọn ìbéèrè yìí: Kí ló jẹ́ ká rí i pé ọkọ àtìyàwó yìí jọ múra ìpadàbẹ̀wò náà sílẹ̀? Kí ni arákùnrin yìí ṣe kí onílé lè rí ìdí tó fi ká Ìwé Mímọ́?
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́: (4 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. (th ẹ̀kọ́ 11)
Ìpadàbẹ̀wò Àkọ́kọ́: (5 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀) Lo ohun tá a lè bá àwọn èèyàn sọ. Lẹ́yìn náà, fún un ní ọ̀kan lára àwọn ìtẹ̀jáde tó wà nínú Àpótí Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́. (th ẹ̀kọ́ 13)
MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Máa Fara Dà Á Tí Wọ́n Bá Hùwà Àìdáa Sí Ẹ Bíi Ti Jósẹ́fù: (6 min.) Ẹ kọ́kọ́ wo fídíò Di Ọ̀rẹ́ Jèhófà—Máa Fara Dà Á Tí Wọ́n Bá Rẹ́ Ẹ Jẹ. Lẹ́yìn náà, pe àwọn ọmọdé mélòó kan wá sórí pèpéle, kó o sì bi wọ́n pé: Báwo ni wọ́n ṣe hùwà àìdáa sí Kọ́lá àti Tósìn? Ẹ̀kọ́ wo lo rò pé wọ́n kọ́ nínú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Jósẹ́fù?
Ohun Tó Ń Fẹ́ Àbójútó Nínú Ìjọ: (9 min.)
Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ: (30 min.) bh orí 19 ¶8-14
Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min. tàbí kó máà tó bẹ́ẹ̀)
Orin 124 àti Àdúrà