ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb24 May ojú ìwé 12-13
  • June 17-23

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • June 17-23
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
mwb24 May ojú ìwé 12-13

JUNE 17-23

SÁÀMÙ 51-53

Orin 89 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Ohun Tó O Lè Ṣe Tó Ò Fi Ní Dẹ́ṣẹ̀ Tó Burú Jáì

(10 min.)

Má ṣe dá ara rẹ lójú jù torí kò sẹ́ni tí ò lè ṣàṣìṣe (Sm 51:5; 2Kọ 11:3)

Máa ṣe ohun táá mú kó o túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà (Sm 51:6; w19.01 15 ¶4-5)

Má ṣe fàyè gba èròkerò àti ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ lọ́kàn rẹ (Sm 51:10-12; w15 6/15 14 ¶5-6)

Àwòrán: Arákùnrin kan tó jẹ́ ọ̀dọ́ ń ṣe àwọn ohun táá mú kó túbọ̀ sún mọ́ Jèhófà. 1. Ó ń ka Bíbélì. 2. Ó ń gbàdúrà gan-an. 3. Ó ń dáhùn nípàdé. 4. Ó ń wàásù níbi àtẹ ìwé.

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 52:2-4—Kí ni àwọn ẹsẹ yìí jẹ́ ká mọ̀ nípa ìwà tí Dóẹ́gì hù? (it-1 644)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sm 51:1-19 (th ẹ̀kọ́ 12)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(2 min.) ÌWÀÁSÙ NÍBI TÍ ÈRÒ PỌ̀ SÍ. (lmd ẹ̀kọ́ 7 kókó 3)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(2 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. (lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 4)

6. Pa Dà Lọ

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Jẹ́ kí ẹni náà mọ orúkọ Ọlọ́run. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 5)

7. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(4 min.) lff ẹ̀kọ́ 14 kókó 7 àti Àwọn Kan Sọ Pé (lmd ẹ̀kọ́ 11 kókó 5)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 115

8. Ohun Tó O Lè Ṣe Tó O Bá Ṣàṣìṣe

(15 min.) Ìjíròrò.

Àwòrán: Àwọn apá kan nínú fídíò “Ìgbà Ọ̀dọ́ Mi—Báwo Ni Mo Ṣe Lè Ṣàtúnṣe?” 1. Thalila. 2. José.

Kò sí bá a ṣe lè ṣe é tá ò fi ní ṣàṣìṣe, ó ṣe tán wọ́n máa ń sọ pé a kì í mọ̀-ọ́n-rìn, kí orí má mì. (1Jo 1:8) Tọ́rọ̀ bá rí bẹ́ẹ̀, a ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí ìtìjú tàbí ìbẹ̀rù ohun tó lè ṣẹlẹ̀ mú ká fà sẹ́yìn láti ṣe ohun tó tọ́. Ó yẹ ká bẹ Jèhófà pé kó dárí jì wá kó sì ràn wá lọ́wọ́. (1Jo 1:9) Ohun àkọ́kọ́ tó yẹ ká ṣe nígbàkigbà tá a bá ṣàṣìṣe ni pé ká gbàdúrà sí Jèhófà.

Ka Sáàmù 51:1, 2, 17. Lẹ́yìn náà béèrè pé:

  • Báwo lohun tí Dáfídì sọ yìí ṣe jẹ́ ká mọ̀ pé Jèhófà ló yẹ ká yíjú sí tá a bá ṣàṣìṣe tó lágbára?

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Ìgbà Ọ̀dọ́ Mi—Báwo Ni Mo Ṣe Lè Ṣàtúnṣe? Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Àwọn nǹkan wo ló mú kí Thalila àti José ṣàṣìṣe?

  • Àwọn nǹkan wo ni wọ́n ṣe kí wọ́n lè ṣàtúnṣe?

  • Àǹfààní wo ni wọ́n rí nígbà tí wọ́n ṣe ohun tó yẹ?

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 11 ¶5-10, àpótí ojú ìwé 89

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 129 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́