ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb24 November ojú ìwé 2-16
  • November 4-10

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • November 4-10
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2024
mwb24 November ojú ìwé 2-16

NOVEMBER 4-10

SÁÀMÙ 105

Orin 3 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

Ilẹ̀ Ìlérí. Àwòrán: 1. Ábúráhámù. 2. Ísákì. 3. Jékọ́bù.

1. “Ó Ń Rántí Májẹ̀mú Rẹ̀ Títí Láé”

(10 min.)

Jèhófà ṣèlérí kan fún Ábúráhámù, ó sì tún ìlérí náà ṣe fún Ísákì àti Jékọ́bù (Jẹ 15:18; 26:3; 28:13; Sm 105:8-11)

Ṣe ló dà bíi pé ìlérí náà ò ní lè ṣẹ (Sm 105:12, 13; w23.04 28 ¶11-12)

Jèhófà ò gbàgbé májẹ̀mú tó bá Ábúráhámù dá (Sm 105:42-44; it-2 1201 ¶2)


BI ARA RẸ PÉ, ‘Àǹfààní wo ló máa ṣe mí tí mo bá fi sọ́kàn pé gbogbo ìlérí Jèhófà ló máa ń ṣẹ?’

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Sm 105:19—Báwo ni “ọ̀rọ̀ Jèhófà” ṣe yọ́ Jósẹ́fù mọ́? (w16.08 23 ¶13)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Sm 105:24-45 (th ẹ̀kọ́ 5)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(1 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Ẹni náà ń ṣiṣẹ́ lọ́wọ́. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

5. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(2 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Dá ọ̀rọ̀ rẹ dúró lọ́nà pẹ̀lẹ́ nígbà tẹ́ni náà bẹ̀rẹ̀ sí í jiyàn. (lmd ẹ̀kọ́ 4 kókó 5)

6. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. Fún ẹni náà ní ìwé ìròyìn tó dá lórí ohun kan tẹ́ni náà nífẹ̀ẹ́ sí nígbà tẹ́ ẹ kọ́kọ́ pàdé. (lmd ẹ̀kọ́ 8 kókó 3)

7. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ ÀÌJẸ́-BÍ-ÀṢÀ. Sọ fún ẹni náà nípa JW Library®, kó o sì bá a wà á sórí fóònù ẹ̀. (lmd ẹ̀kọ́ 9 kókó 5)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 84

8. Ọ̀nà Tó O Lè Gbà Fìfẹ́ Hàn

(15 min.) Ìjíròrò.

Tá a bá ń fi àkókò wa, okun wa àti owó wa ti iṣẹ́ Ọlọ́run lẹ́yìn, ṣe là ń fi hàn pé a nífẹ̀ẹ́ Kristi Jésù, Ọba tí Jèhófà yàn. Tá a bá ń fi ìfẹ́ wa hàn lọ́nà yìí, inú Jèhófà á dùn sí wa, àwọn ará wa sì máa jàǹfààní. (Jo 14:23) Àwọn àpilẹ̀kọ tá a pè ní “Bá A Ṣe Ń Ná Owó Tẹ́ Ẹ Fi Ń Ṣètọrẹ” lórí ìkànnì jw.org máa ń jẹ́ ká rí bí owó tá a fi ń ṣètìlẹyìn ṣe ń ran àwọn ará wa lọ́wọ́ kárí ayé.

Àwòrán ọwọ́ ẹni tó ń fi owó sínú àpótí ọrẹ. Àwòrán: 1. Arákùnrin kan dúró síwájú adájọ́. 2. Arábìnrin kan ń bá àwọn tó ń kọ ilé ètò Ọlọ́run ṣiṣẹ́. 3. Arábìnrin kan ń wo fídíò tí wọ́n ṣe fáwọn adití

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Iṣẹ́ Kékeré Kọ́ Ni Ìtìlẹyìn Yín Ń Ṣe. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Báwo ni owó ìtìlẹyìn tá à ń ná ká lè jọ́sìn Ọlọ́run fàlàlà ṣe ń ṣe àwọn ará wa láǹfààní?

  • Àǹfààní wo la ti rí bá a ṣe ń mú ‘kí nǹkan dọ́gba’ tó bá dọ̀rọ̀ ìtìlẹyìn táwọn ará ń ṣe ká lè kọ́ àwọn Ilé Ìpàdé wa kárí ayé?—2Kọ 8:14

  • Àǹfààní wo la ti rí bá a ṣe ń lo owó tẹ́ ẹ fi ń ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ ìtumọ̀ Bíbélì?

Mọ Púpọ̀ Sí I Lórí Ìkànnì

Àmì “Ọrẹ“ tó jẹ́ ọwọ́ tó mówó dání.

Àwọn ọ̀nà wo lo lè gbà fowó ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń ṣe kárí ayé? Tẹ ìlujá “Donations” tó wà nísàlẹ̀ ibi tó o máa kọ́kọ́ rí tó o bá ṣí JW Library. Ní ọ̀pọ̀ orílẹ̀-èdè, wàá rí ìlujá kan tá a pè ní FAQ, ìyẹn Ìbéèrè Táwọn Èèyàn Máa Ń Béèrè. Tó o bá tẹ̀ ẹ́, á gbé àpilẹ̀kọ kan jáde tá a pè ní Donations to Jehovah’s Witnesses—Frequently Asked Questions.

9. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) bt orí 17 ¶13-19

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 97 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́