ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb25 November ojú ìwé 14-15
  • December 22-28

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • December 22-28
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2025
mwb25 November ojú ìwé 14-15

DECEMBER 22-28

ÀÌSÁYÀ 11-13

Orin 14 àti Àdúrà | Ọ̀rọ̀ Ìbẹ̀rẹ̀ (1 min.)

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN

1. Kí Ni Bíbélì Jẹ́ Ká Mọ̀ Nípa Ẹni Tó Máa Jẹ́ Mèsáyà Náà?

(10 min.)

Ó máa jẹ́ àtọmọdọ́mọ Jésè nípasẹ̀ ọmọ rẹ̀ Dáfídì (Ais 11:1; ip-1 159 ¶4-5)

Ẹ̀mí Jèhófà lá máa darí ẹ̀, á sì máa ṣe nǹkan lọ́nà tí Jèhófà fẹ́ (Ais 11:2, 3a; ip-1 159 ¶6; 160 ¶8)

Ó máa ṣèdájọ́ lọ́nà tó tọ́, á sì tún fàánú hàn tó bá ń ṣèdájọ́ (Ais 11:3b-5; ip-1 160 ¶9; 161 ¶11)

Jésù ń ṣàkóso ní ọ̀run, ó na ọwọ́ ẹ̀ sí ayé tó ti di Párádísè.

RONÚ LÓRÍ ÌBÉÈRÈ YÌÍ: Kí ló máa mú kí ìṣàkóso Jésù dáa ju tèèyàn lọ?

2. Àwọn Ẹ̀kọ́ Iyebíye Míì

(10 min.)

  • Ais 11:10—Báwo ni àsọtẹ́lẹ̀ yìí ṣe nímùúṣẹ? (ip-1 165-166 ¶16-18)

  • Àwọn ẹ̀kọ́ iyebíye wo lo rí nínú Bíbélì kíkà ọ̀sẹ̀ yìí tí wàá fẹ́ sọ?

3. Bíbélì Kíkà

(4 min.) Ais 11:1-12 (th ẹ̀kọ́ 11)

TẸRA MỌ́ IṢẸ́ ÌWÀÁSÙ

4. Bá A Ṣe Lè Bẹ̀rẹ̀ Ọ̀rọ̀ Wa

(3 min.) ÌWÀÁSÙ ILÉ-DÉ-ILÉ. (lmd ẹ̀kọ́ 2 kókó 5)

5. Pa Dà Lọ

(4 min.) ÌWÀÁSÙ NÍBI TÍ ÈRÒ PỌ̀ SÍ. Lo ìkànnì jw.org láti dáhùn ìbéèrè ẹni náà. (lmd ẹ̀kọ́ 8 kókó 3)

6. Sọ Àwọn Èèyàn Di Ọmọ Ẹ̀yìn

(5 min.) Ran ẹni tó ò ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́ lọ́wọ́ láti mọ bó ṣe lè wàásù láti ilé dé ilé. (lmd ẹ̀kọ́ 11 kókó 4)

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Orin 57

7. Ṣé O Kì Í “Fi Ìrísí Òde Ṣe Ìdájọ́”?

(15 min.) Ìjíròrò.

Arákùnrin méjì ń wàásù fún ọkùnrin kan tó rí fìrìgbọ̀n, tó sì fín àwòrán oríṣiríṣi sára. Èyí tó jẹ́ ọ̀dọ́ fi fídíò “Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì?” han ọkùnrin náà. Àwòrán àwọn tó máa ń kọ orin oníwà ipá wà lára ògiri ẹ̀.

Lọ́pọ̀ ìgbà, ohun tá a bá rí la fi máa ń pinnu irú ẹni tí ẹnì kan jẹ́ àtohun tó máa ṣe. Àmọ́ ní ti Jésù, ohun tó fojú rí kọ́ ló fi máa ń ṣèdájọ́, ó sì yẹ ká tẹ̀ lé àpẹẹrẹ ẹ̀. (Ais 11:3, 4) Jésù mọ ohun tó wà lọ́kàn èèyàn, bí ẹni náà ṣe ń ronú àtohun tó ń mú kó ṣe nǹkan. Àmọ́, àwa ò lè mọ àwọn nǹkan yìí. Síbẹ̀, ó yẹ ká gbìyànjú láti fara wé Jésù. Jésù sọ pé: “Ẹ yéé fi ìrísí òde ṣe ìdájọ́, àmọ́ ẹ máa dá ẹjọ́ òdodo.”—Jo 7:24.

Lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, tó bá jẹ́ pé bí ẹnì kan ṣe rí la fi ń pinnu irú ẹni tó jẹ́, a ò ní ṣe iṣẹ́ ìwàásù wa dáadáa, ìtara wa sì máa dín kù. Bí àpẹẹrẹ, tá a bá dé ibì kan tí àwọn tó ń gbé níbẹ̀ wá láti ẹ̀yà míì tàbí tí ẹ̀sìn wọn yàtọ̀, ṣé ó máa ń yá wa lára láti wàásù níbẹ̀? Tó bá jẹ́ àdúgbò táwọn olówó tàbí àwọn tálákà pọ̀ sí ńkọ́? Ṣé a máa ń ronú pé ẹnì kan ò ní gbọ́ ìwàásù torí bó ṣe rí? Ohun tí Ọlọ́run fẹ́ ni pé “ká gba onírúurú èèyàn là, kí wọ́n sì ní ìmọ̀ tó péye nípa òtítọ́.”—1Ti 2:4.

Jẹ́ kí àwọn ará wo FÍDÍÒ Àwọn Ẹ̀kọ́ Látinú Ilé Ìṣọ́—Má Ṣe Máa Fi Ìrísí Dáni Lẹ́jọ́. Lẹ́yìn náà, béèrè pé:

  • Bá a ṣe rí i nínú fídíò yìí, àwọn nǹkan wo ló ń mú káwọn èèyàn máa fi ojú pa àwọn míì rẹ́?

  • Kí ló lè ṣẹlẹ̀ tá a bá gba ẹ̀mí burúkú yìí láyè nínú ìjọ?

  • Kí ló ran àwọn tá a fọ̀rọ̀ wá lẹ́nu wò lọ́wọ́ tí wọn ò fi fi ìrísí dá àwọn míì lẹ́jọ́?

  • Kí lo kọ́ nínú àpilẹ̀kọ Ilé Ìṣọ́ yẹn?

8. Ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ìjọ

(30 min.) lfb ẹ̀kọ́ 46-47

Ọ̀rọ̀ Ìparí (3 min.) | Orin 12 àti Àdúrà

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́