ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • nwt ojú ìwé 931-934
  • Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Àìsáyà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Àìsáyà
  • Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Orúkọ Tuntun” Kan
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
  • Ohun Tí Jèhófà Pinnu Láti Ṣe sí Àwọn Orílẹ̀-Èdè
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kìíní
  • “Ẹ Fi Ìdùnnú Ké Jáde ní Ìsopọ̀ṣọ̀kan”!
    Àsọtẹ́lẹ̀ Aísáyà—Ìmọ́lẹ̀ fún Gbogbo Aráyé, Apá Kejì
  • Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Sáàmù
    Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Àwọn Míì
Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun
Ohun Tó Wà Nínú Ìwé Àìsáyà

ÀÌSÁYÀ

OHUN TÓ WÀ NÍNÚ ÌWÉ YÌÍ

  • 1

    • Bàbá kan àti àwọn ọmọ rẹ̀ tó ya ọlọ̀tẹ̀ (1-9)

    • Jèhófà kórìíra ìjọsìn ojú lásán (10-17)

    • “Ẹ jẹ́ ká yanjú ọ̀rọ̀” (18-20)

    • Síónì máa pa dà di ìlú olóòótọ́ (21-31)

  • 2

    • A gbé òkè Jèhófà ga (1-5)

      • Wọ́n á fi idà rọ ohun ìtúlẹ̀ (4)

    • Ọjọ́ Jèhófà máa tẹ àwọn agbéraga lórí ba (6-22)

  • 3

    • Àwọn olórí Júdà kó àwọn èèyàn ṣìnà (1-15)

    • A dá àwọn ọmọbìnrin Síónì oníṣekúṣe lẹ́jọ́ (16-26)

  • 4

    • Obìnrin méje máa di ọkùnrin kan mú (1)

    • Ohun tí Jèhófà mú kó rú jáde máa ní ògo (2-6)

  • 5

    • Orin nípa ọgbà àjàrà Jèhófà (1-7)

    • Ó mà ṣe fún ọgbà àjàrà Jèhófà o (8-24)

    • Ọlọ́run bínú sí àwọn èèyàn rẹ̀ (25-30)

  • 6

    • Ìran nípa Jèhófà nínú tẹ́ńpìlì rẹ̀ (1-4)

      • “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Jèhófà” (3)

    • A wẹ ètè Àìsáyà mọ́ (5-7)

    • Àìsáyà gba iṣẹ́ (8-10)

      • “Èmi nìyí! Rán mi!” (8)

    • “Títí dìgbà wo, Jèhófà?” (11-13)

  • 7

    • A ránṣẹ́ sí Ọba Áhásì (1-9)

      • Ṣeari-jáṣúbù (3)

    • Ohun tí a fi máa dá Ìmánúẹ́lì mọ̀ (10-17)

    • Ohun tó máa gbẹ̀yìn ìwà àìṣòótọ́ (18-25)

  • 8

    • Ásíríà máa gbé ogun wá (1-8)

      • Maheri-ṣalali-háṣí-básì (1-4)

    • Ẹ má bẹ̀rù⁠—“Ọlọ́run wà pẹ̀lú wa!” (9-17)

    • Àìsáyà àti àwọn ọmọ rẹ̀ máa jẹ́ àmì (18)

    • Ẹ yíjú sí òfin, kì í ṣe sí àwọn ẹ̀mí èṣù (19-22)

  • 9

    • Ìmọ́lẹ̀ tó tàn yòò fún ilẹ̀ Gálílì (1-7)

      • A bí “Ọmọ Aládé Àlàáfíà” (6-7)

    • Ọwọ́ Ọlọ́run máa kọ lu Ísírẹ́lì (8-21)

  • 10

    • Ọwọ́ Ọlọ́run máa kọ lu Ísírẹ́lì (1-4)

    • Ásíríà⁠—​Ọ̀pá ìbínú Ọlọ́run (5-11)

    • Ìyà tó máa jẹ Ásíríà (12-19)

    • Àṣẹ́kù Jékọ́bù máa pa dà (20-27)

    • Ọlọ́run máa dá Ásíríà lẹ́jọ́ (28-34)

  • 11

    • Èéhù Jésè máa fi òdodo ṣàkóso (1-10)

      • Ìkookò máa bá ọmọ àgùntàn gbé (6)

      • Ìmọ̀ Jèhófà máa bo ayé (9)

    • Àṣẹ́kù pa dà (11-16)

  • 12

    • Orin ìdúpẹ́ (1-6)

      • “Jáà Jèhófà ni okun mi” (2)

  • 13

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Bábílónì (1-22)

      • Ọjọ́ Jèhófà sún mọ́lé! (6)

      • Àwọn ará Mídíà máa ṣẹ́gun Bábílónì (17)

      • Wọn ò ní gbé inú Bábílónì mọ́ láé (20)

  • 14

    • Ísírẹ́lì máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ (1, 2)

    • Wọ́n fi ọba Bábílónì ṣe ẹlẹ́yà (3-23)

      • Ẹni tó ń tàn máa já bọ́ láti ọ̀run (12)

    • Ọwọ́ Jèhófà máa fọ́ ará Ásíríà túútúú (24-27)

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Filísíà (28-32)

  • 15

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Móábù (1-9)

  • 16

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Móábù ń bá a lọ (1-14)

  • 17

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Damásíkù (1-11)

    • Jèhófà máa bá àwọn orílẹ̀-èdè wí (12-14)

  • 18

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Etiópíà (1-7)

  • 19

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Íjíbítì (1-15)

    • Íjíbítì máa mọ Jèhófà (16-25)

      • Pẹpẹ kan máa wà fún Jèhófà ní Íjíbítì (19)

  • 20

    • Àmì àti àpẹẹrẹ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ sí Íjíbítì àti Etiópíà (1-6)

  • 21

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí aginjù òkun (1-10)

      • Ó ń ṣọ́nà láti orí ilé ìṣọ́ (8)

      • “Bábílónì ti ṣubú!” (9)

    • Ìkéde lòdì sí Dúmà àti aṣálẹ̀ tó tẹ́jú (11-17)

      • “Olùṣọ́, báwo ni òru ṣe rí?” (11)

  • 22

    • Ìkéde nípa Àfonífojì Ìran (1-14)

    • Wọ́n fi Élíákímù rọ́pò Ṣébínà tó jẹ́ ìríjú (15-25)

      • Èèkàn tó ṣàpẹẹrẹ ohun kan (23-25)

  • 23

    • Ọ̀rọ̀ ìkéde sí Tírè (1-18)

  • 24

    • Jèhófà máa sọ ilẹ̀ náà di òfìfo (1-23)

      • Jèhófà di Ọba ní Síónì (23)

  • 25

    • Ọlọ́run máa bù kún àwọn èèyàn rẹ̀ lọ́pọ̀ yanturu (1-12)

      • Àkànṣe àsè Jèhófà tó ní wáìnì tó dáa (6)

      • Kò ní sí ikú mọ́ (8)

  • 26

    • Orin ìgbẹ́kẹ̀lé àti ìgbàlà (1-21)

      • Jáà Jèhófà, Àpáta ayérayé (4)

      • Àwọn tó ń gbé ayé máa kọ́ òdodo (9)

      • “Àwọn òkú rẹ máa wà láàyè” (19)

      • Ẹ wọ àwọn yàrá inú, kí ẹ sì fara pa mọ́ (20)

  • 27

    • Jèhófà pa Léfíátánì (1)

    • Orin tó fi Ísírẹ́lì wé ọgbà àjàrà (2-13)

  • 28

    • Ó mà ṣe fún àwọn ọ̀mùtípara Éfúrémù o! (1-6)

    • Àwọn àlùfáà àti wòlíì Júdà ń ta gọ̀ọ́gọ̀ọ́ (7-13)

    • Wọ́n “bá Ikú dá májẹ̀mú” (14-22)

      • Òkúta igun tó ṣeyebíye ní Síónì (16)

      • Iṣẹ́ Jèhófà tó ṣàjèjì (21)

    • Bí Jèhófà ṣe ń fi ọgbọ́n báni wí (23-29)

  • 29

    • O gbé, ìwọ Áríélì! (1-16)

      • Ọlọ́run dẹ́bi fún àwọn tó ń fi ẹnu lásán sìn ín (13)

    • Adití máa gbọ́rọ̀; afọ́jú sì máa ríran (17-24)

  • 30

    • Íjíbítì ò lè ṣèrànwọ́ kankan (1-7)

    • Àwọn èèyàn ò fetí sí àsọtẹ́lẹ̀ (8-14)

    • Ìgbẹ́kẹ̀lé máa fi hàn pé wọ́n lágbára (15-17)

    • Jèhófà ṣojúure sí àwọn èèyàn rẹ̀ (18-26)

      • Jèhófà, Olùkọ́ni Atóbilọ́lá (20)

      • “Èyí ni ọ̀nà” (21)

    • Jèhófà máa dá Ásíríà lẹ́jọ́ (27-33)

  • 31

    • Ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run ló dájú, kì í ṣe ti èèyàn (1-9)

      • Ẹran ara ni àwọn ẹṣin Íjíbítì (3)

  • 32

    • Ọba kan àti àwọn ìjòyè máa ṣàkóso fún ìdájọ́ òdodo (1-8)

    • A kìlọ̀ fún àwọn obìnrin tí ara tù (9-14)

    • Tí a bá tú ẹ̀mí jáde, ó máa mú ìbùkún wá (15-20)

  • 33

    • Ìdájọ́ àti ìrètí fún àwọn olódodo (1-24)

      • Jèhófà ni Onídàájọ́, Afúnnilófin àti Ọba (22)

      • Kò sẹ́ni tó máa sọ pé: “Ara mi ò yá” (24)

  • 34

    • Jèhófà máa gbẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè (1-4)

    • Édómù máa di ahoro (5-17)

  • 35

    • Ayé pa dà di Párádísè (1-7)

      • Afọ́jú máa ríran; adití máa gbọ́ràn (5)

    • Ọ̀nà Ìjẹ́mímọ́ fún àwọn tí a tún rà (8-10)

  • 36

    • Senakérúbù gbéjà ko Júdà (1-3)

    • Rábúṣákè pẹ̀gàn Jèhófà (4-22)

  • 37

    • Hẹsikáyà ní kí Àìsáyà bá òun bẹ Ọlọ́run fún ìrànlọ́wọ́ (1-7)

    • Senakérúbù halẹ̀ mọ́ Jerúsálẹ́mù (8-13)

    • Àdúrà tí Hẹsikáyà gbà (14-20)

    • Àìsáyà sọ ohun tí Ọlọ́run sọ (21-35)

    • Áńgẹ́lì kan pa 185,000 àwọn ọmọ Ásíríà (36-38)

  • 38

    • Hẹsikáyà ṣàìsàn, ara rẹ̀ sì yá (1-22)

      • Orin ìdúpẹ́ (10-20)

  • 39

    • Àwọn ìránṣẹ́ láti Bábílónì (1-8)

  • 40

    • A tu àwọn èèyàn Ọlọ́run nínú (1-11)

      • Ohùn kan nínú aginjù (3-5)

    • Ọlọ́run tóbi (12-31)

      • Àwọn orílẹ̀-èdè dà bí ẹ̀kán omi kan látinú korobá (15)

      • Ọlọ́run ń gbé orí “òbìrìkìtì ayé” (22)

      • Ó ń fi orúkọ pe gbogbo ìràwọ̀ (26)

      • Kì í rẹ Ọlọ́run (28)

      • Ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Jèhófà ń mú kéèyàn jèrè okun pa dà (29-31)

  • 41

    • Aṣẹ́gun kan láti ìlà oòrùn (1-7)

    • Ọlọ́run yan Ísírẹ́lì pé kó jẹ́ ìránṣẹ́ òun (8-20)

      • “Ábúráhámù ọ̀rẹ́ mi” (8)

    • Ó pe àwọn ọlọ́run míì níjà (21-29)

  • 42

    • Ìránṣẹ́ Ọlọ́run àti ohun tó máa ṣe (1-9)

      • ‘Jèhófà ni orúkọ mi’ (8)

    • Orin ìyìn tuntun sí Jèhófà (10-17)

    • Ísírẹ́lì fọ́jú, ó sì dití (18-25)

  • 43

    • Jèhófà pa dà kó àwọn èèyàn rẹ̀ jọ (1-7)

    • Kí àwọn ọlọ́run gbèjà ara wọn (8-13)

      • “Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi” (10, 12)

    • Wọ́n máa tú wọn sílẹ̀ láti Bábílónì (14-21)

    • “Jẹ́ ká gbé ẹjọ́ wa wá” (22-28)

  • 44

    • Ọlọ́run máa bù kún àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ (1-5)

    • Kò sí Ọlọ́run míì àfi Jèhófà (6-8)

    • Àwọn òrìṣà tí èèyàn ṣe kò já mọ́ nǹkan kan (9-20)

    • Jèhófà, Olùtúnrà Ísírẹ́lì (21-23)

    • Ipasẹ̀ Kírúsì ni wọ́n máa pa dà (24-28)

  • 45

    • Ọlọ́run yan Kírúsì pé kó ṣẹ́gun Bábílónì (1-8)

    • Amọ̀ ò lè bá Amọ̀kòkò fà á (9-13)

    • Àwọn orílẹ̀-èdè míì mọ Ísírẹ́lì (14-17)

    • Ọlọ́run ṣeé gbára lé lórí ọ̀rọ̀ ìṣẹ̀dá àti ṣíṣí nǹkan payá (18-25)

      • Ó dá ayé ká lè máa gbé inú rẹ̀ (18)

  • 46

    • Àwọn òrìṣà Bábílónì àti Ọlọ́run Ísírẹ́lì (1-13)

      • Jèhófà ń sọ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ lọ́jọ́ iwájú (10)

      • Ẹyẹ aṣọdẹ láti ìlà oòrùn (11)

  • 47

    • Ìṣubú Bábílónì (1-15)

      • Àṣírí àwọn awòràwọ̀ tú (13-15)

  • 48

    • Ọlọ́run bá Ísírẹ́lì wí, ó sì wẹ̀ ẹ́ mọ́ (1-11)

    • Jèhófà máa kọ lu Bábílónì (12-16a)

    • Ẹ̀kọ́ Ọlọ́run ṣàǹfààní (16b-19)

    • “Ẹ jáde kúrò ní Bábílónì!” (20-22)

  • 49

    • Iṣẹ́ ìránṣẹ́ Jèhófà (1-12)

      • Ìmọ́lẹ̀ àwọn orílẹ̀-èdè (6)

    • A tu Ísírẹ́lì nínú (13-26)

  • 50

    • Àwọn ẹ̀ṣẹ̀ Ísírẹ́lì fa wàhálà (1-3)

    • Ìránṣẹ́ Jèhófà tó jẹ́ onígbọràn (4-11)

      • Ahọ́n àti etí àwọn tí a kọ́ (4)

  • 51

    • Síónì máa pa dà rí bí ọgbà Édẹ́nì (1-8)

    • Aṣẹ̀dá Síónì tó lágbára tù wọ́n nínú (9-16)

    • Ife ìbínú Jèhófà (17-23)

  • 52

    • Jí, ìwọ Síónì! (1-12)

      • Ẹsẹ̀ àwọn tó ń mú ìhìn rere wá rẹwà (7)

      • Àwọn olùṣọ́ Síónì kígbe níṣọ̀kan (8)

      • Àwọn tó ń gbé àwọn ohun èlò Jèhófà gbọ́dọ̀ mọ́ (11)

    • A máa gbé ìránṣẹ́ Jèhófà ga (13-15)

      • Wọ́n ba ìrísí rẹ̀ jẹ́ (14)

  • 53

    • Ìyà tó máa jẹ ìránṣẹ́ Jèhófà, bó ṣe máa kú àti bí wọ́n ṣe máa sin ín (1-12)

      • Wọ́n kórìíra rẹ̀, wọ́n sì yẹra fún un (3)

      • Ó gbé àìsàn àti ìrora (4)

      • “Bí àgùntàn sí ibi tí wọ́n ti fẹ́ pa á” (7)

      • Ó ru ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀pọ̀ èèyàn (12)

  • 54

    • Síónì tó yàgàn máa ní ọmọ púpọ̀ (1-17)

      • Jèhófà, ọkọ Síónì (5)

      • Jèhófà máa kọ́ àwọn ọmọ Síónì (13)

      • Ohun ìjà tí wọ́n bá ṣe sí Síónì kò ní ṣàṣeyọrí (17)

  • 55

    • Ìkésíni láti jẹ, kí wọ́n sì mu lọ́fẹ̀ẹ́ (1-5)

    • Ẹ wá Jèhófà àti ọ̀rọ̀ rẹ̀ tó ṣeé gbára lé (6-13)

      • Ọ̀nà Ọlọ́run ga ju ti èèyàn lọ (8, 9)

      • Ó dájú pé ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa yọrí sí rere (10, 11)

  • 56

    • Àwọn àjèjì àti àwọn ìwẹ̀fà máa rí ìbùkún (1-8)

      • Ilé àdúrà fún gbogbo èèyàn (7)

    • Àwọn olùṣọ́ tó fọ́jú, ajá tí kò lè fọhùn (9-12)

  • 57

    • Olódodo àti àwọn olóòótọ́ ṣègbé (1, 2)

    • Àgbèrè ẹ̀sìn tí Ísírẹ́lì ń ṣe hàn síta (3-13)

    • A tu àwọn ẹni rírẹlẹ̀ nínú (14-21)

      • Àwọn ẹni burúkú dà bí òkun tó ń ru (20)

      • Kò sí àlàáfíà fún ẹni burúkú (21)

  • 58

    • Ààwẹ̀ tó dénú àti èyí tí kò dénú (1-12)

    • Pípa Sábáàtì mọ́ ń múnú ẹni dùn (13, 14)

  • 59

    • Àwọn ẹ̀ṣẹ̀ Ísírẹ́lì mú kí wọ́n jìnnà sí Ọlọ́run (1-8)

    • Wọ́n jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ (9-15a)

    • Jèhófà dá sí i torí àwọn tó ronú pìwà dà (15b-21)

  • 60

    • Ògo Jèhófà tàn sórí Síónì (1-22)

      • Bí àwọn àdàbà tó ń fò lọ sí ilé wọn (8)

      • Wúrà dípò bàbà (17)

      • Ẹni tó kéré máa di ẹgbẹ̀rún (22)

  • 61

    • A fòróró yàn án láti kéde ìhìn rere (1-11)

      • “Ọdún ìtẹ́wọ́gbà Jèhófà” (2)

      • “Igi ńlá òdodo” (3)

      • Àwọn àjèjì máa ṣèrànwọ́ (5)

      • “Àlùfáà Jèhófà” (6)

  • 62

    • Orúkọ tuntun tí Síónì á máa jẹ́ (1-12)

  • 63

    • Jèhófà máa gbẹ̀san lára àwọn orílẹ̀-èdè (1-6)

    • Bí Jèhófà ṣe fi ìfẹ́ tí kì í yẹ̀ hàn nígbà àtijọ́ (7-14)

    • Àdúrà ìrònúpìwàdà (15-19)

  • 64

    • Àdúrà ìrònúpìwàdà ń bá a lọ (1-12)

      • Jèhófà, “Ẹni tó mọ wá” (8)

  • 65

    • Jèhófà máa dá àwọn abọ̀rìṣà lẹ́jọ́ (1-16)

      • Ọlọ́run Oríire àti Àyànmọ́ (11)

      • “Àwọn ìránṣẹ́ mi máa jẹun” (13)

    • Ọ̀run tuntun àti ayé tuntun (17-25)

      • A máa kọ́ ilé; a máa gbin ọgbà àjàrà (21)

      • Kò sẹ́ni tó máa ṣiṣẹ́ àṣedànù (23)

  • 66

    • Ìjọsìn tòótọ́ àti ìjọsìn èké (1-6)

    • Síónì tó jẹ́ ìyá àti àwọn ọmọ rẹ̀ (7-17)

    • Àwọn èèyàn kóra jọ láti jọ́sìn ní Jerúsálẹ́mù (18-24)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́