ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g 10/11 ojú ìwé 2
  • Ojú Ìwé Kejì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ojú Ìwé Kejì
  • Jí!—2011
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Kọ́ Ọmọ Rẹ Láti Ìgbà Ọmọdé Jòjòló
    Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé
  • Wá Ìmọ̀ràn Tó Dáa Gbà
    Jí!—2007
  • Ojúṣe Rẹ Gẹ́gẹ́ bí Òbí
    Jí!—2004
  • Ẹ̀yin Òbí, Ẹ Ran Àwọn Ọmọ Yín Lọ́wọ́ Kí Wọ́n Lè Nífẹ̀ẹ́ Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
Àwọn Míì
Jí!—2011
g 10/11 ojú ìwé 2

Ojú Ìwé Kejì

Bí Àwọn Òbí Ṣe Lè Tọ́ Àwọn Ọmọ Yanjú

Ohun kan wà tí àwọn òbí kì í sábà ronú nípa rẹ̀ tí wọ́n bá ń wo ọmọ wọn jòjòló. Àmọ́ òótọ́ pọ́ńbélé ni pé: Ní àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀ ọmọ wọn jòjòló yìí máa dàgbà di géńdé, ó sì máa wà láyè ara rẹ̀. Bí Ọlọ́run sì ṣe fẹ́ kó rí gan-an nìyẹn, torí Bíbélì sọ pé ‘ọkùnrin yóò fi baba rẹ̀ àti ìyá rẹ̀ sílẹ̀.’ (Jẹ́nẹ́sísì 2:24) Bẹ́ẹ̀ náà ló ṣe máa ń rí fún àwọn ọ̀dọ́bìnrin.

Síbẹ̀, ní ọjọ́ ayọ̀ tí ojú sábà máa ń roni yẹn, ìyẹn ní ọjọ́ tí ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin tó ti dàgbà bá fi ilé sílẹ̀, ọ̀pọ̀ òbí sábà máa ń ronú pé: ‘Ǹjẹ́ mo tọ́ ọmọ mi bó ṣe tọ́?’ ‘Ṣé ó máa lè fọwọ́ pàtàkì mú iṣẹ́ rẹ̀, ṣé á mọ ilé tọ́jú, ṣé kò sì ní máa ná ìnákúnàá?’ Èyí tó wá ṣe pàtàkì jù ni pé, ‘Ṣé ọmọ mi á lè máa tẹ̀ lé ìlànà ìwà rere tá a ti kọ́ ọ?’​—Òwe 22:6; 2 Tímótì 3:15.

Àkànṣe ìwé ìròyìn Jí! yìí ṣàlàyé bí ìmọ̀ràn Bíbélì ṣe lè ran àwọn òbí lọ́wọ́ láti bójú tó àwọn ọmọ wọn bí wọ́n ṣe ń dàgbà.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́