ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g16 No. 4 ojú ìwé 4
  • 1 Má Tan Ara Rẹ

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • 1 Má Tan Ara Rẹ
  • Jí!—2016
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jẹ́ Kí Àwọn Àṣà Tó Ti Mọ́ Ọ Lára Ṣe Ọ́ Láǹfààní
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
  • Ìgbọ́rọ̀kalẹ̀
    Jí!—2016
  • Ǹjẹ́ Ó Ṣeé Ṣe Láti Jáwọ́ Nínú Àṣà Burúkú?
    Jí!—2004
  • 2 Kíyè Sí Ohun Tó Ń Lọ Láyìíká Rẹ
    Jí!—2016
Àwọn Míì
Jí!—2016
g16 No. 4 ojú ìwé 4
Obìnrin tó ń kọ̀wé

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | ÀWỌN ÀṢÀ TÓ LÈ ṢE Ẹ́ LÁǸFÀÀNÍ

1 Má Tan Ara Rẹ

Ó sábà máa ń wù wá láti ṣe gbogbo àtúnṣe tó yẹ nígbèésí ayé wa lẹ́ẹ̀kan náà. Nígbà míì, èèyàn lè sọ pé, ‘Lọ́sẹ̀ yìí, mi ò ní mu sìgá mọ́, mi ò ní ṣépè mọ́, mi ò ní pẹ́ kí n tó lọ sùn, màá bẹ̀rẹ̀ sí í ṣeré ìmárale, màá máa jẹun gidi, màá sì máa pe àwọn òbí mi àgbà.’ Tó o bá gbìyànjú láti ṣe gbogbo àtúnṣe yìí lẹ́ẹ̀kan náà, ńṣe lo máa dà bí ẹni tó ń lé eku méjì, o ò wá ní rí ìkankan ṣe!

ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ: “Ọgbọ́n wà pẹ̀lú àwọn amẹ̀tọ́mọ̀wà.”—Òwe 11:2.

Ẹni tó jẹ́ amẹ̀tọ́mọ̀wà máa ń mọ ohun tí agbára òun gbé. Ó mọ̀ pé ó ní ìwọ̀nba nǹkan tí òun lè fi àkókò, okun àti ohun ìní òun ṣe. Torí náà, dípò tí á fi máa fẹ́ láti ṣe gbogbo àtúnṣe yìí lẹ́ẹ̀kan náà, díẹ̀díẹ̀ ni á máa ṣe é.

Tó o bá gbìyànjú láti ṣe gbogbo àtúnṣe yìí lẹ́ẹ̀kan náà, ńṣe lo máa dà bí ẹni tó ń lé eku méjì, o ò wá ní rí ìkankan ṣe!

OHUN TÓ O LÈ ṢE

Díẹ̀díẹ̀ ni kó o máa ṣe àwọn àtúnṣe tó bá yẹ. Àwọn àbá yìí lè ràn ẹ́ lọ́wọ́:

  1. Wá ìwé méjì, kọ àwọn ìwà rere tó o fẹ́ máa hù sínú ọ̀kan, kó o sì kọ àwọn àṣà tí ò dáa tó o fẹ́ jáwọ́ nínú rẹ̀ sínú ìkejì. Kọ gbogbo ohun tó o fẹ́ ṣe lórí apá méjèèjì láìṣẹ́ ku ohunkóhun.

  2. Èyí tó o kọ́kọ́ fẹ́ ṣe ni kó o kọ ṣáájú nínú gbogbo rẹ̀.

  3. O lè kọ́kọ́ mú àṣà kan tàbí méjì nínú ìwé méjèèjì, ìyẹn sì ni kó o gbájú mọ́. Tó bá tún yá, mú méjì míì tí wàá tún ṣiṣẹ́ lé lórí.

Ohun tó máa jẹ́ kí àtúnṣe náà yára ni pé kó o fi àwọn àṣà tó dáa rọ́pò èyí tí kò dáa. Bí àpẹẹrẹ, tó bá jẹ́ pé àwòjù tẹlifíṣọ̀n wà lára àṣà tó o fẹ́ jáwọ́ nínú rẹ̀, tó sì tún wù ẹ́ láti máa wáyè fáwọn èèyàn rẹ, o lè pinnu pé: ‘Dípò kí n gba ìdí tẹlifíṣọ̀n lọ ní gbàrà tí mo délé, màá kúkú fóònù àwọn ọ̀rẹ́ tàbí àwọn ẹbí mi.’

ÀWỌN ÌLÀNÀ BÍBÉLÌ MÍÌ

“Máa wádìí dájú àwọn ohun tí ó ṣe pàtàkì jù.”​—Fílípì 1:10.

“Òpin ọ̀ràn kan ní àsẹ̀yìnwá-àsẹ̀yìnbọ̀ sàn ju ìbẹ̀rẹ̀pẹ̀pẹ̀ rẹ̀ lọ.”​—Oníwàásù 7:8.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́