ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • g20 No. 2 ojú ìwé 4-5
  • Ohun Táwọn Kan Gbà Gbọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Táwọn Kan Gbà Gbọ́
  • Jí!—2020
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Ẹlẹ́sìn Híńdù
  • Àwọn Mùsùlùmí
  • Àwọn Ẹlẹ́sìn Júù
  • Àwọn Ẹlẹ́sìn Búdà
  • Àwọn Ẹlẹ́sìn Confucius
  • Àwọn Ẹlẹ́sìn Ìbílẹ̀
  • Àwọn Kristẹni
  • Ohun Tí Bíbélì Sọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
  • Ìbéèrè Kẹta: Kí Nìdí Tí Ọlọ́run Fi Jẹ́ Kí Ìyà Máa Jẹ Mí?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • 4. Ṣé Látìbẹ̀rẹ̀ Ni Ọlọ́run Ti Dá Wa Pé Ká Máa Jìyà?
    Jí!—2020
  • Ìyà
    Jí!—2015
Àwọn Míì
Jí!—2020
g20 No. 2 ojú ìwé 4-5
Àmì ẹ̀sìn Búdà, ẹ̀sìn Híńdù, ẹ̀sìn ìbílẹ̀, ẹ̀sìn àwọn Júù, ẹ̀sìn Kristẹni, ẹ̀sìn Ìsìláàmù àti ẹ̀sìn Confucius.

Ohun Táwọn Kan Gbà Gbọ́

Àwọn Ẹlẹ́sìn Híńdù

Àmì ẹ̀sìn Híńdù.

Wọ́n gbà gbọ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ tẹ́nì kan ń dá báyìí tàbí èyí tó dá nígbà tó kọ́kọ́ wá sáyé ló fa ìyà tó ń jẹ ẹ́. Kí ẹni náà tó lè bọ́ lọ́wọ́ ìyà, ó dìgbà tó bá dé ìpele tí wọ́n ń pè ní moksha, ìyẹn ni ìgbà tí kò ní tún ayé wá mọ́. Nígbà yẹn kò ní ro ohun ti ayé mọ́.

Àwọn Mùsùlùmí

Àmì ẹ̀sìn Ìsìláàmù.

Wọ́n gbà gbọ́ pé ìyà jẹ́ èrè ẹ̀ṣẹ̀ àti àdánwò ìgbàgbọ́. Ọ̀jọ̀gbọ́n Sayyid Syeed, tó jẹ́ ààrẹ Islamic Society of North America sọ pé àwọn àjálù ń rán wa létí pé “ká máa dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run nítorí àwọn oore tó ń ṣe fún wa, ó sì tún ń rán wa létí pé ká máa ran àwọn aláìní lọ́wọ́.”

Àwọn Ẹlẹ́sìn Júù

Àmì ẹ̀sìn àwọn Júù.

Wọ́n gbà gbọ́ pé àfọwọ́fà ni ìyà tó ń jẹ èèyàn. Àwọn Júù kan sọ pé àjíǹde máa wà, lẹ́yìn náà ni àwọn aláìṣẹ̀ tó ń jìyà máa gba ìdájọ́ òdodo. Àwọn ẹlẹ́sìn Júù tó gbà gbọ́ nínú agbára abàmì gbà pé àtúnwáyé wà, èyí tó máa fún ẹnì kan láǹfààní láti ṣètùtù fún àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.

Àwọn Ẹlẹ́sìn Búdà

Àmì ẹ̀sìn Búdà.

Wọ́n gbà gbọ́ pé ẹnì kan á máa jìyà ní gbogbo ìgbà tó bá tún ayé wá àfìgbà tẹ́ni náà bá jáwọ́ nínú ìwà, èrò àti ìfẹ́ ọkàn tí kò dáa. Wọ́n tún sọ pé téèyàn bá ní ọgbọ́n, tó ń ṣiṣẹ́ òdodo, tó sì ń kó èrò rẹ̀ níjàánu, ó máa dé ìpele nirvana, ìyẹn ìgbà tí gbogbo ìyà ẹni náà máa dópin.

Àwọn Ẹlẹ́sìn Confucius

Àmì ẹ̀sìn Confucius.

Ìwé kan tó ń jẹ́ Dictionary of Comparative Religion sọ pé àwọn ẹlẹ́sìn Confucius gbà gbọ́ pé “ẹ̀ṣẹ̀ àti àṣìṣe èèyàn” ló ń fa èyí tó pọ̀ jù nínú ìyà tó ń jẹ aráyé. Ẹ̀kọ́ ẹ̀sìn wọn sọ pé èèyàn lè dín ìyà náà kù tó bá ń gbé ìgbé ayé òdodo, àmọ́ àwọn “ẹ̀mí tó lágbára ju èèyàn ló lè mú ìyà náà kúrò. Nírú ipò bẹ́ẹ̀ àfi kéèyàn fara mọ́ ohun tí kádàrá ẹ̀ bá sọ.”

Àwọn Ẹlẹ́sìn Ìbílẹ̀

Àmì ẹ̀sìn ìbílẹ̀.

Wọ́n gbà gbọ́ pé àwọn ẹlẹ́mìí òkùnkùn ló ń fa ìyà. Ìgbàgbọ́ wọn ni pé àwọn àjẹ́ lè mú kéèyàn ṣoríire tàbí kí wọ́n ba tèèyàn jẹ́, àfi kéèyàn ṣe ètùtù láti tù wọ́n lójú. Torí náà, nígbà tí ẹnì kan bá ń ṣàìsàn, àwọn babaláwo máa ń rúbọ tàbí kí wọ́n ṣe oògùn téèyàn lè fi ṣẹ́gun àwọn àjẹ́ náà.

Àwọn Kristẹni

Àmì ẹ̀sìn Kristẹni.

Wọ́n gbà gbọ́ pé ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ẹ̀dá méjì tí Ọlọ́run kọ́kọ́ dá ló fa ìyà, gẹ́gẹ́ bí Bíbélì ṣe sọ nínú ìwé Jẹ́nẹ́sísì. Ọ̀pọ̀ ẹ̀ka ẹ̀sìn Kristẹni ló ti ṣe àbùmọ́ ẹ̀kọ́ yìí. Bí àpẹẹrẹ, àwọn Kátólíìkì sọ pé èèyàn lè fara jìyà láti fi tọrọ ìbùkún Ọlọ́run sórí ìjọ tàbí pé kó wo ọlá ìyà tẹ́nì kan jẹ láti gba ẹlòmíì là.

TÓ O BÁ FẸ́ MỌ̀ SÍ I

Wo fídíò náà Ṣé Gbogbo Ẹ̀sìn Ni Ọlọ́run Tẹ́wọ́ Gbà? Ó wà lórí jw.org.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́