ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • my ìtàn 18
  • Jékọ́bù Lọ Sí Háránì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jékọ́bù Lọ Sí Háránì
  • Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jékọ́bù Mọyì Àwọn Nǹkan Tẹ̀mí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Àwọn Tẹ̀gbọ́n-tàbúrò Tí wọn Ò Láyọ̀ Ló “Kọ́ Ilé Ísírẹ́lì”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Jékọ́bù Ní Ìdílé Ńlá
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Ìgbà Wo Ni Jèhófà Máa Ń Bù Kún—Ìsapá Tí A Fi Taratara Ṣe?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
Àwọn Míì
Ìwé Ìtàn Bíbélì
my ìtàn 18
Jékọ́bù ń bá àwọn ará Háránì sọ̀rọ̀ nípa Lábánì àti Rákélì ọmọbìnrin rẹ̀

ÌTÀN 18

Jékọ́bù Lọ Sí Háránì

ǸJẸ́ o mọ àwọn tí Jékọ́bù ń bá sọ̀rọ̀ yìí? Lẹ́yìn tí Jékọ́bù ti rin ìrìn àjò fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọjọ́, ó pàdé àwọn èèyàn wọ̀nyí lẹ́bàá kànga kan. Wọ́n ń tọ́jú àgùntàn wọn. Jékọ́bù béèrè lọ́wọ́ wọn pé: ‘Ibo lẹ ti wá?’

Wọ́n dáhùn pé: ‘Ìlú Háránì ni.’

Jékọ́bù béèrè pé: ‘Ǹjẹ́ ẹ mọ Lábánì?’

Wọ́n dáhùn pé, ‘Bẹ́ẹ̀ ni. Wò ó, Rákélì, ọmọbìnrin rẹ̀, ló ń da agbo àgùntàn bàbá rẹ̀ bọ̀ yìí.’ Ṣé o rí Rákélì tó ń bọ̀ lọ́ọ̀ọ́kán?

Rákélì ń tọ́jú àwọn àgùntàn bàbá rẹ̀

Nígbà tí Jékọ́bù rí Rákélì pẹ̀lú àwọn àgùntàn Lábánì ẹ̀gbọ́n ìyá rẹ̀, ó lọ yí òkúta kúrò lẹ́nu kànga kí àwọn àgùntàn náà lè mu omi. Lẹ́yìn náà, Jékọ́bù fẹnu ko Rákélì lẹ́nu ó sì sọ ẹni tí òun jẹ́ fún un. Inú Rákélì dùn gidigidi, ó sáré lọ sí ilé ó sì sọ fún Lábánì bàbá rẹ̀.

Inú Lábánì dùn sí i pé kí Jékọ́bù máa bá òun gbé. Nígbà tí Jékọ́bù sọ pé òun fẹ́ fẹ́ Rákélì, inú Lábánì dùn gan-an. Ṣùgbọ́n, ó sọ pé kí Jékọ́bù ṣiṣẹ́ nínú oko òun fún ọdún méje kó tó lè fẹ́ Rákélì. Jékọ́bù gbà láti ṣe bẹ́ẹ̀ nítorí pé ó fẹ́ràn Rákélì gan-an. Ṣùgbọ́n nígbà tí àkókò ìgbéyàwó tó, ǹjẹ́ o mọ ohun tó ṣẹlẹ̀?

Ṣe ni Lábánì fi Léà ọmọbìnrin rẹ̀ tó jẹ́ ẹ̀gbọ́n fún Jékọ́bù dípò Rákélì. Nígbà tí Jékọ́bù gbà láti ṣiṣẹ́ sin Lábánì fún ọdún méje mìíràn sí i, Lábánì tún fún un ní Rákélì láti fi ṣe aya. Ní ìgbà yẹn lọ́hùn-ún, Ọlọ́run gbà káwọn ọkùnrin máa ní ju ìyàwó kan lọ. Ṣùgbọ́n nísinsìnyí, gẹ́gẹ́ bí Bíbélì ṣe fi hàn, ìyàwó kan ṣoṣo ni ọkùnrin kan gbọ́dọ̀ ní.

Jẹ́nẹ́sísì 29:1-30.

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́