ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • my ìtàn 90
  • Pẹ̀lú Obìnrin Kan Lẹ́bàá Kànga

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Pẹ̀lú Obìnrin Kan Lẹ́bàá Kànga
  • Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Obìnrin kan Wá Pọn Omi Nínú Kànga
    Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Kíkọ́ Obinrin Ara Samaria Kan Lẹkọọ
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Jésù Kọ́ Obìnrin Ará Samáríà Kan Lẹ́kọ̀ọ́
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Omi Tó Ń Tú Yàà Sókè Láti Fúnni Ní Ìyè Àìnípẹ̀kun
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
Àwọn Míì
Ìwé Ìtàn Bíbélì
my ìtàn 90
Jésù ń bá obìnrin ará Samáríà sọ̀rọ̀ ní etí kàǹga

ÌTÀN 90

Pẹ̀lú Obìnrin Kan Lẹ́bàá Kànga

JÉSÙ dúró sinmi lẹ́bàá kànga kan ní Samáríà. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn rẹ̀ ti lọ láti ra oúnjẹ nínú ìlú. Omi ni obìnrin tí Jésù ń bá sọ̀rọ̀ yìí wá pọn. Jésù wí fún un pé: ‘Fún mi ní omi mu.’

Èyí ya obìnrin yẹn lẹ́nu púpọ̀. Ǹjẹ́ o mọ ìdí rẹ̀? Ìdí ni pé Júù ni Jésù, ará Samáríà sì ni obìnrin yìí. Ọ̀pọ̀ jù lọ àwọn Júù ni ò sì fẹ́ràn àwọn ará Samáríà. Wọn kì í tiẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀! Àmọ́ Jésù fẹ́ràn gbogbo onírúurú èèyàn. Torí náà, ó sọ pé: ‘Ká ní o mọ ẹni tó ń tọrọ omi lọ́wọ́ rẹ ni, wàá tọrọ omi iyè lọ́wọ́ rẹ̀ á sì fún ẹ ní omi tó ń fún èèyàn ní ìyè.’

Obìnrin yẹn sọ pé: ‘Ọ̀gá, kànga yìí jìn púpọ̀ o, bẹ́ẹ̀ ẹ sì tún ní garawa. Ibo lẹ ti máa rí omi tó ń fún èèyàn ní ìyè yìí?’

Jésù ṣàlàyé fún un pé: ‘Bó o bá mu omi inú kànga yìí, òùngbẹ á ṣì máa gbẹ ọ́. Àmọ́ omi tí màá fún èèyàn lè mú kéèyàn wà láàyè títí láé.’

Obìnrin yẹn wí pé: ‘Ọ̀gá, ẹ jọ̀wọ́, ẹ fún mi ní omi tẹ́ ẹ̀ ń wí yìí! Nípa bẹ́ẹ̀, òùngbẹ ò tún ní gbẹ mí mọ́. Mi ò sì tún ní máa wá síbí wá pọn omi mọ́.’

Omi gidi ni obìnrin yẹn rò pé Jésù ń sọ. Àmọ́ òtítọ́ nípa Ọlọ́run àti Ìjọba Ọlọ́run ni Jésù ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Ṣe ni òtítọ́ yìí dà bí omi tó ń fún èèyàn ní ìyè. Ó lè fún èèyàn ní ìyè àìnípẹ̀kun.

Ni Jésù bá sọ fún obìnrin yẹn pé: ‘Lọ pe ọkọ rẹ wá.’

Obìnrin náà dáhùn pé: ‘Mi ò ní ọkọ.’

Jésù sọ pé: ‘Òótọ́ ni ìdáhùn rẹ. Ṣùgbọ́n o ti ní ọkọ márùn-ún rí, ọkùnrin tó o sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀ nísinsìnyí kì í ṣe ọkọ rẹ.’

Ẹnu ya obìnrin yìí gidigidi torí pé òtítọ́ ni gbogbo èyí. Báwo ni Jésù ṣe mọ gbogbo nǹkan yìí? Jésù mọ̀ ọ́n torí pé Jésù ni Ẹni Ìlérí náà tí Ọlọ́run rán wá, Ọlọ́run ló sì sọ gbogbo nǹkan wọ̀nyí fún un. Àkókò yìí làwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù dé, ẹnu sì yà wọ́n pé ó ń bá obìnrin ará Samáríà sọ̀rọ̀.

Kí ni gbogbo èyí kọ́ wa? Ó fi hàn pé Jésù máa ń ṣe dáadáa sí gbogbo onírúurú èèyàn. Àwa náà sì gbọ́dọ̀ jẹ́ onínúure pẹ̀lú. Kò yẹ ká máa ronú pé àwọn èèyàn kan ò dáa nítorí pé wọ́n wá látinú ìran tàbí ẹ̀yà míì. Jésù fẹ́ kí gbogbo èèyàn mọ òtítọ́ tó ń sinni lọ sí ìyè àìnípẹ̀kun. Àwa náà sì gbọ́dọ̀ nífẹ̀ẹ́ sí i láti ran àwọn èèyàn lọ́wọ́ kí wọ́n lè kẹ́kọ̀ọ́ òtítọ́.

Jòhánù 4:5-43; 17:3.

Àwọn Ìbéèrè fún Ìkẹ́kọ̀ọ́

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́