Ẹ̀KỌ́ 10
Ẹ Rántí Aya Lọ́ọ̀tì
Ọ̀dọ̀ Ábúráhámù tó jẹ́ àbúrò bàbá Lọ́ọ̀tì ni Lọ́ọ̀tì ń gbé nílẹ̀ Kénáánì. Bọ́jọ́ ṣe ń gorí ọjọ́, ẹran ọ̀sìn Ábúráhámù àti Lọ́ọ̀tì pọ̀ gan-an débi pé ibi tí wọ́n ń gbé ò gbà wọ́n mọ́. Ábúráhámù wá sọ fún Lọ́ọ̀tì pé: ‘A ò ní lè jọ máa gbé pa pọ̀ mọ́. Torí náà, jọ̀ọ́ yan apá ibi tó wù ẹ́ láti lọ, kémi náà sì lọ síbòmíì.’ Ṣé ohun tí Ábúráhámù ṣe yẹn dáa àbí kò dáa?
Lọ́ọ̀tì rí apá ibì kan ní ilẹ̀ náà tó dáa gan-an, ibẹ̀ ò jìnnà sí ìlú Sódómù. Koríko táwọn ẹran lè jẹ pọ̀ níbẹ̀, omi sì wà níbẹ̀ dáadáa. Bí òun àti ìdílé ẹ̀ ṣe kó lọ síbẹ̀ nìyẹn.
Ìwà àwọn èèyàn ìlú Sódómù àti Gòmórà tó wà nítòsí rẹ̀ burú gan-an. Kódà ìwà wọn burú débi pé Jèhófà sọ pé òun máa pa àwọn ìlú náà run. Àmọ́, Jèhófà fẹ́ gba Lọ́ọ̀tì àti ìdílé rẹ̀ là, torí náà ó rán áńgẹ́lì méjì pé kí wọ́n lọ kìlọ̀ fún wọn. Àwọn áńgẹ́lì yẹn sọ fún wọn pé: ‘Ó yá, ẹ ṣe kíá! Ẹ jáde kúrò nílùú yìí torí Jèhófà máa tó pa ìlú yìí run.’
Àmọ́ Lọ́ọ̀tì kò tètè dá wọn lóhùn. Ṣé o mọ ohun táwọn áńgẹ́lì yẹn ṣe? Wọ́n fa Lọ́ọ̀tì, ìyàwó rẹ̀ àtàwọn ọmọbìnrin wọn méjèèjì lọ́wọ́, wọ́n sì mú wọn jáde kúrò nílùú náà. Wọ́n wá sọ fún wọn pé: ‘Ó yá! Ẹ máa sá lọ, ẹ má wẹ̀yìn o. Tẹ́ ẹ bá wẹ̀yìn, ikú ni o!’
Nígbà tí wọ́n dé ìlú kan tó ń jẹ́ Sóárì, Jèhófà rọ òjò iná àti imí ọjọ́ sórí ìlú Sódómù àti Gòmórà. Ìlú méjèèjì yẹn jóná pátápátá. Ìyàwó Lọ́ọ̀tì ṣe ohun tí Jèhófà ní wọn ò gbọ́dọ̀ ṣe, ó bojú wẹ̀yìn, ó sì di ọwọ̀n iyọ̀! Àmọ́ Lọ́ọ̀tì àtàwọn ọmọbìnrin ẹ̀ kò kú torí pé wọ́n ṣègbọràn sí Jèhófà. Ó dájú pé inú wọn ò ní dùn pé màmá wọn ṣàìgbọràn sí Jèhófà. Àmọ́ inú wọn á dùn pé àwọn ṣe ohun tí Jèhófà sọ.
“Ẹ rántí aya Lọ́ọ̀tì.”—Lúùkù 17:32