MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI
Ẹ Rántí Aya Lọ́ọ̀tì
Kí nìdí tí aya Lọ́ọ̀tì fi bojú wẹ̀yìn bó ṣe ń sá kúrò nílùú Sódómù? Bíbélì ò sọ ìdí. (Jẹ 19:17, 26) Ìkìlọ̀ tí Jésù ṣe fi hàn pé ó ṣeé ṣe kí ọkàn rẹ̀ má kúrò nínú àwọn nǹkan tó fi sílẹ̀. (Lk 17:31, 32) Báwo làwa náà ò ṣe ní pàdánù ojú rere Ọlọ́run bíi ti aya Lọ́ọ̀tì? A ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí eré bá a ṣe máa kó àwọn ohun amáyédẹrùn jọ gbà wá lọ́kàn. (Mt 6:33) Jésù kọ́ wa pé a “kò lè sìnrú fún Ọlọ́run àti fún Ọrọ̀.” (Mt 6:24) Àmọ́, kí la lè ṣe tá a bá fura pé kíkó ohun ìní jọ ti bẹ̀rẹ̀ sí í gbà wá lọ́kàn débi tá ò fi ráyè fún àwọn nǹkan tẹ̀mí mọ́? A lè gbàdúrà sí Jèhófà pé kó fún wa ní ọgbọ́n láti rí àwọn ibi tó ti yẹ ká ṣàtúnṣe, ká sì nígboyà àti okun láti ṣe bẹ́ẹ̀.
ṢÓ O RÁNTÍ FÍDÍÒ ALÁPÁ MẸ́TA NÁÀ Ẹ RÁNTÍ AYA LỌ́Ọ̀TÌ? Ó YÁ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:
Báwo ni ìwà àti ìṣe mi ṣe lè fi hàn pé mò ń “rántí aya Lọ́ọ̀tì”?
Báwo ni bí wọ́n ṣe ń fúngun mọ́ Gloria láti túbọ̀ kó owó jọ ṣe kó bá bó ṣe ń ronú, bó ṣe ń sọ̀rọ̀, àti ìwà rẹ̀?
Báwo ni aya Lọ́ọ̀tì ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ tó yẹ ká yẹra fún lónìí?
Báwo ni ìlànà Bíbélì tí Joe àti ìdílé rẹ̀ fi sílò ṣe ràn wọ́n lọ́wọ́?
Báwo làwọn tí Anna ń bá kẹ́gbẹ́ ní ibiṣẹ́ ṣe ṣàkóbá fún un nípa tẹ̀mí?
Kí nìdí tá a fi nílò ìgboyà nígbà tí wọ́n bá ń fúngun mọ́ wa pé ká wá bá a ṣe máa rí towó ṣe?
Báwo ni Brian àti Gloria ṣe pa dà fi àjọṣe wọn pẹ̀lú Jèhófà sípò àkọ́kọ́?
Ìlànà Bíbélì wo lo rí nínú fídíò yìí?