ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 26 ojú ìwé 66-ojú ìwé 67 ìpínrọ̀ 1
  • Àwọn Amí Méjìlá

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Amí Méjìlá
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Àwọn Amí Méjìlá
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Iwọ Ha Ń Tọ Jehofa Lẹhin Lẹ́kùn-ún-rẹ́rẹ́ Bi?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1993
  • Ohun Tí Jóṣúà Rántí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Fi Gbogbo Ọkàn Rẹ Gbẹ́kẹ̀ Lé Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 26 ojú ìwé 66-ojú ìwé 67 ìpínrọ̀ 1
Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ ṣe amí ilẹ̀ Kénáánì

Ẹ̀KỌ́ 26

Àwọn Amí Méjìlá

Nígbà táwọn ọmọ Ísírẹ́lì kúrò ní Òkè Sínáì, wọ́n rin ìrìn àjò gba àwọn aṣálẹ̀ Páránì lọ sí ibì kan tó ń jẹ́ Kádéṣì. Níbẹ̀, Jèhófà sọ fún Mósè pé: ‘Rán ọkùnrin méjìlá (12) látinú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti lọ ṣe amí ilẹ̀ Kénáánì, ilẹ̀ yìí ni màá fún ẹ̀yin ọmọ Ísírẹ́lì.’ Torí náà, Mósè yan ọkùnrin méjìlá (12), ó sì sọ fún wọn pé: ‘Ẹ lọ yẹ ilẹ̀ Kénáánì wò bóyá ó dáa fun iṣé àgbẹ̀. Kẹ́ ẹ sì wo báwọn èèyàn ibẹ̀ ṣe lágbára tó, bóyá inú àgọ́ ni wọ́n ń gbé tàbí ìlú ńlá.’ Jóṣúà àti Kélẹ́bù wà lára àwọn amí méjìlá náà, gbogbo wọn sì gba ilẹ̀ Kénáánì lọ.

Àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ráhùn, wọ́n sì rẹ̀wẹ̀sì

Àwọn amí yìí pa dà lẹ́yìn ogójì (40) ọjọ́, wọ́n sì kó ọ̀pọ̀tọ́, pómégíránétì àti èso àjàrà wálé. Wọ́n sọ pé: ‘Ilẹ̀ náà dáa, àmọ́ àwọn èèyàn ibẹ̀ lágbára gan-an, ògiri wọn sì tún ga gìrìwò.’ Kélẹ́bù wá sọ pé: ‘A lè ṣẹ́gun wọn. Ẹ jẹ́ ká lọ mú wọn balẹ̀ báyìí!’ Ṣé o mọ ìdí tí Kélẹ́bù fi sọ̀rọ̀ bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé òun àti Jóṣúà gbẹ́kẹ̀ lé Ọlọ́run. Àmọ́ àwọn amí mẹ́wàá tó kù sọ pé: ‘Rárá! Àwa ò ní tẹ̀ lé yín lọ síbì kankan. Àwọn ará ìlú yẹn ga gan-an, wọ́n sì lágbára! Ńṣe la dà bíi kòkòrò kékeré lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.’

Inú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì bà jẹ́. Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í ráhùn, wọ́n sì ń sọ fún ara wọn pé: ‘Ẹ jẹ́ ká yan ẹlòmíì táá máa darí wa, ká sì pa dà sí Íjíbítì. Kí ló dé tá a fi máa gba ilẹ̀ Kénáánì lọ kí wọ́n lè pa wá dà nù?’ Jóṣúà àti Kélẹ́bù sọ pé: ‘Ẹ má ṣàìgbọràn sí Jèhófà, ẹ má sì bẹ̀rù rárá. Jèhófà máa dáàbò bò wá.’ Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ò gbọ́. Àní wọ́n tiẹ̀ fẹ́ pa Jóṣúà àti Kélẹ́bù!

Kí ni Jèhófà wá ṣe? Ó sọ fún Mósè pé: ‘Pẹ̀lú gbogbo ohun tí mo ṣe fáwọn ọmọ Ísírẹ́lì, síbẹ̀ wọn ò gbọ́ràn sí mi lẹ́nu. Torí ohun tí wọ́n ṣe yìí, wọn ò ní kúrò nínú aṣálẹ̀ yìí fún ogójì (40) ọdún, ibẹ̀ ni wọ́n sì máa kú sí. Àwọn ọmọ wọn pẹ̀lú Jóṣúà àti Kélẹ́bù ló máa gba ilẹ̀ tí mo ṣèlérí pé màá fún un yín.’

“Kí ló dé tí ẹ̀rù ń bà yín tó báyìí, ẹ̀yin tí ìgbàgbọ́ yín kéré?”​—Mátíù 8:26

Ìbéèrè: Kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà táwọn amí méjìlá (12) náà pa dà dé láti ilẹ̀ Kénáánì? Báwo ni Jóṣúà àti Kélẹ́bù ṣe fi hàn pé àwọn gbẹ́kẹ̀ lé Jèhófà?

Nọ́ńbà 13:1–14:38; Diutarónómì 1:22-33; Sáàmù 78:22; Hébérù 3:17-19

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́