ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 35 ojú ìwé 86-ojú ìwé 87 ìpínrọ̀ 1
  • Hánà Gbàdúrà Pé Kí Ọlọ́run Fún Òun ní Ọmọkùnrin

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Hánà Gbàdúrà Pé Kí Ọlọ́run Fún Òun ní Ọmọkùnrin
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ó Sọ Ẹ̀dùn Ọkàn Rẹ̀ fún Ọlọ́run Nínú Àdúrà
    Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Ìgbàgbọ́ Wọn
  • Obìnrin Náà Gbàdúrà Àtọkànwá sí Ọlọ́run
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Bí Hánà Ṣe Dẹni Tó Ní Ìbàlẹ̀ Ọkàn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Jẹ́ Kí Jèhófà Tù Ẹ́ Lára
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 35 ojú ìwé 86-ojú ìwé 87 ìpínrọ̀ 1
Hánà mú Sámúẹ́lì lọ sọ́dọ̀ Élì ní àgọ́ ìjọsìn

Ẹ̀KỌ́ 35

Hánà Gbàdúrà Pé Kí Ọlọ́run Fún Òun ní Ọmọkùnrin

Ọmọ Ísírẹ́lì kan wà tórúkọ ẹ̀ ń jẹ́ Ẹlikénà. Ìyàwó méjì ló fẹ́. Hánà àti Pẹ̀nínà lorúkọ wọn, àmọ́ Hánà ló fẹ́ràn jù. Pẹ̀nínà máa ń fi Hánà ṣe yẹ̀yẹ́ torí pé kò rọ́mọ bí, àmọ́ Pẹ̀nínà bímọ tó pọ̀ ní tiẹ̀. Lọ́dọọdún, Ẹlikénà máa ń kó ìdílé ẹ̀ lọ sí àgọ́ ìjọsìn ní Ṣílò kí wọ́n lè lọ jọ́sìn Jèhófà. Lọ́jọ́ kan tí wọ́n wà ní Ṣílò, ó kíyè sí i pé inú Hánà ìyàwó ẹ̀ ò dùn rárá. Ó wá sọ pé: ‘Hánà jọ̀ọ́ má sunkún mọ́. Bó ò bá tiẹ̀ bímọ, fọkàn balẹ̀. Mo nífẹ̀ẹ́ ẹ.’

Nígbà tó yá, Hánà lọ dá gbàdúrà. Bó ṣe ń gbàdúrà pé kí Jèhófà ran òun lọ́wọ́ ló ṣáà ń sunkún. Ó ṣèlérí pé: ‘Jèhófà, tó o bá fún mi ní ọmọkùnrin, ìwọ ni màá fún, ó sì máa fi gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ sìn ẹ́.’

Élì Àlùfáà Àgbà ń wo Hánà bó ṣe ń sunkún nígbà tó ń gbàdúrà

Élì Àlùfáà Àgbà rí i pé Hánà ń sunkún, ó sì ronú pé ó ti mutí yó. Hánà dáhùn pé: ‘Rárá Olúwa mi, mi ò mutí yó. Mo níṣòro ńlá kan ni, mo sì ń bá Jèhófà sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀.’ Élì wá rí i pé èrò òun ò dáa, ló bá sọ fún un pé: ‘Kí Ọlọ́run fún ẹ lóhun tó o tọrọ lọ́wọ́ ẹ̀.’ Ara tu Hánà, ó sì bá ọ̀nà ẹ̀ lọ. Kò pé ọdún kan lẹ́yìn náà tó fi bí ọmọkùnrin kan, ó sì pe orúkọ ẹ̀ ní Sámúẹ́lì. Ṣé o mọ bínú Hánà ṣe máa dùn tó?

Hánà ò gbàgbé ìlérí tó ṣe fún Jèhófà. Bí Hánà ṣe rí i pé Sámúẹ́lì ti dàgbà díẹ̀, ó mú un lọ sí àgọ́ ìjọsìn kó lè máa sin Jèhófà níbẹ̀. Ó sọ fún Élì pé: ‘Ọmọkùnrin tí mo tọrọ lọ́wọ́ Ọlọ́run nìyí. Mo ti yọ̀ǹda ẹ̀ fún Jèhófà títí láé.’ Ọdọọdún ni Ẹlikénà àti Hánà máa ń lọ wo Sámúẹ́lì, wọ́n á sì mú aṣọ kékeré tí kò lápá lọ fún un. Jèhófà tún wá fún Hánà ní ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì míì.

“Ẹ máa béèrè, a sì máa fún yín; ẹ máa wá kiri, ẹ sì máa rí.”​—Mátíù 7:7

Ìbéèrè: Kí ló fà á tí inú Hánà ò fi dùn? Báwo ni Jèhófà ṣe bù kún Hánà?

1 Sámúẹ́lì 1:1–2:11, 18-21

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́