ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 51 ojú ìwé 124-ojú ìwé 125 ìpínrọ̀ 2
  • Jagunjagun àti Ọmọbìnrin Kékeré Kan

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jagunjagun àti Ọmọbìnrin Kékeré Kan
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ọmọbìnrin Kan Ran Ọkọ Ọ̀gá Rẹ̀ Lọ́wọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Ó Kọ́kọ́ Ṣàìgbọràn àmọ́ Nígbà Tó Yá Ó Ṣègbọràn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2012
  • Ọmọbìnrin Kan Ran Ọkùnrin Alágbára Kan Lọ́wọ́
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
  • Ọmọbìnrin Kékeré Kan Tí Ó Fìgboyà Sọ̀rọ̀
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 51 ojú ìwé 124-ojú ìwé 125 ìpínrọ̀ 2
Náámánì lọ sọ́dọ̀ Èlíṣà kó lè rí ìwòsàn

Ẹ̀KỌ́ 51

Jagunjagun àti Ọmọbìnrin Kékeré Kan

Ọmọbìnrin Ísírẹ́lì kan wà nílẹ̀ Síríà, ibẹ̀ sì jìnnà gan-an sílùú ẹ̀. Àwọn ọmọ ogun Síríà ni wọ́n mú un kúrò lọ́dọ̀ àwọn òbí ẹ̀, wọ́n sì sọ ọ́ di ìránṣẹ́ ìyàwó ọ̀gágun kan tó ń jẹ́ Náámánì. Jèhófà ni ọmọbìnrin yìí ń jọ́sìn bó tiẹ̀ jẹ́ pé abọ̀rìṣà làwọn tó yí i kà.

Náámánì ní àìsàn burúkú kan tó máa ń jẹ́ kí ara ro ó. Ó sì wu ọmọbìnrin yìí pé kóun ran Náámánì lọ́wọ́. Ó wá sọ fún ìyàwó Náámánì pé: ‘Mo mọ ẹnì kan tó lè ran ọkọ yín lọ́wọ́. Ilẹ̀ Ísírẹ́lì lẹni náà wà, wòlíì Jèhófà ni, Èlíṣà sì lorúkọ ẹ̀. Ó lè wo ọkọ yín sàn.’

Nígbà tí ìyàwó Náámánì sọ̀rọ̀ ọmọbìnrin yìí fún Náámánì, ó gbà pé òun á lọ bá Èlíṣà ní Ísírẹ́lì. Náámánì rò pé tóun bá dé Ísírẹ́lì, ńṣe ni Èlíṣà máa ṣe òun bí èèyàn pàtàkì. Àmọ́ Èlíṣà ò tiẹ̀ yọjú sí Náámánì rárá, ìránṣẹ́ ẹ̀ ló rán sí i. Ó ní kó lọ pàdé Náámánì, kó sì sọ fún un pé: ‘Lọ wẹ̀ nínú Odò Jọ́dánì nígbà méje, àìsàn ẹ sì máa lọ.’

Ọ̀rọ̀ yìí bí Náámánì nínú gan-an. Ló bá ní: ‘Mo rò pé ńṣe ni wòlíì yìí á gbàdúrà fún mi táá gbọ́wọ́ lé mi lórí, tára mi á sì yá. Ó wá ń sọ pé kí n lọ wẹ̀ lódò kan ní Ísírẹ́lì. Ṣèbí a ní odò tó dáa jùyẹn lọ ní Síríà, kí ló dé tí ò lè sọ pé kí n lọ wẹ̀ níbẹ̀?’ Inú bí Náámánì gan-an débi pé ńṣe ló fìbínú kúrò nílé Èlíṣà.

Náámánì wẹ̀ nínú Odò Jọ́dánì, ó sì rí ìwòsàn

Ni àwọn ìránṣẹ́ Náámánì bá sọ ohun tó mú kó tún ọ̀rọ̀ náà rò. Wọ́n sọ fún un pé: ‘Tó bá jẹ́ pé ohun tí wòlíì yẹn sọ ló máa mú yín lára dá, ṣé kò ní dáa kẹ́ ẹ ṣe é? Ohun tí wòlíì yìí sì ní kẹ́ ẹ ṣe ò le rárá, á dáa kẹ́ ẹ ṣe é.’ Náámánì fetí sí wọn. Ó lọ sí Odò Jọ́dánì, ó sì wẹ̀ níbẹ̀ nígbà méje. Nígbà tí Náámánì fi máa jáde nínú odò nígbà keje, àìsàn tó ń ṣe é ti lọ. Inú ẹ̀ dùn gan-an, ó sì pa dà lọ dúpẹ́ lọ́wọ́ Èlíṣà. Náámánì sọ pé: ‘Mo ti wá mọ̀ pé Jèhófà ni Ọlọ́run tòótọ́.’ Báwo ló ṣe máa rí lára ọmọbìnrin Ísírẹ́lì yẹn nígbà tó rí i pé ara Náámánì ti yá?

“Láti ẹnu àwọn ọmọdé àti àwọn ọmọ jòjòló lo ti mú kí ìyìn jáde.”​—Mátíù 21:16

Ìbéèrè: Ṣé o rò pé ó rọrùn fún ọmọbìnrin Ísírẹ́lì yẹn láti bá ìyàwó Náámánì sọ̀rọ̀? Kí lo rò pé ó jẹ́ kó nígboyà?

2 Àwọn Ọba 5:1-19; Lúùkù 4:27

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́