ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • lfb ẹ̀kọ́ 93 ojú ìwé 216-ojú ìwé 217 ìpínrọ̀ 5
  • Jésù Pa Dà sí Ọ̀run

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Jésù Pa Dà sí Ọ̀run
  • Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ọ̀pọ̀ Èèyàn Ló Rí Jésù Ṣáájú Ọjọ́ Pẹ́ńtíkọ́sì
    Jésù—Ọ̀nà, Òtítọ́ Àti Ìyè
  • Awọn Ifarahan Ikẹhin, Ati Pẹntikọsti 33 C.E.
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Awọn Ifarahan Ikẹhin, ati Pẹntikọsi 33 C.E.
    Ọkunrin Titobilọla Julọ Ti O Tii Gbé Ayé Rí
  • Lórí Òkè Ólífì
    Ìwé Ìtàn Bíbélì
Àwọn Míì
Àwọn Ẹ̀kọ́ Tó O Lè Kọ́ Látinú Bíbélì
lfb ẹ̀kọ́ 93 ojú ìwé 216-ojú ìwé 217 ìpínrọ̀ 5
Jésù ń gòkè lọ sọ́run, àwọn àpọ́sítélì ẹ̀ sì ń wò ó

Ẹ̀KỌ́ 93

Jésù Pa Dà sí Ọ̀run

Nígbà tí Jésù wà pẹ̀lú àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ ní Gálílì, ó gbé iṣẹ́ pàtàkì kan lé wọn lọ́wọ́. Ó pàṣẹ fún wọn pé: ‘Ẹ lọ, kẹ́ ẹ sì máa sọ àwọn èèyàn gbogbo orílẹ̀-èdè di ọmọ ẹ̀yìn. Ẹ máa kọ́ wọn ní ohun tí mo ti kọ́ ọ yín, kẹ́ ẹ sì ṣèrìbọmi fún wọn.’ Jésù wá ṣèlérí pé, ‘òun máa wà pẹ̀lú wọn.’

Láàárín ogójì (40) ọjọ́ lẹ́yìn tí Jésù jí dìde, ó fara han àwọn ọmọ ẹ̀yìn tó pọ̀ ní Gálílì àti Jerúsálẹ́mù. Ó kọ́ wọn láwọn ẹ̀kọ́ pàtàkì, ó sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ ìyanu. Àwọn àpọ́sítélì ẹ̀ wá bá a lórí Òkè Ólífì fúngbà ìkẹyìn, ó sì sọ fún wọn pé: ‘Ẹ dúró ní Jerúsálẹ́mù kẹ́ ẹ sì máa retí ohun tí Baba ṣèlérí.’

Àmọ́ ohun tó ń sọ ò yé àwọn àpọ́sítélì ẹ̀. Wọ́n wá béèrè pé: ‘Ṣó o ti fẹ́ di Ọba Ísírẹ́lì báyìí ni?’ Jésù dáhùn pé: ‘Kò tíì tó àkókò tí Jèhófà yàn fún mi láti di Ọba. Ṣùgbọ́n láìpẹ́, ẹ̀mí mímọ́ máa fún yín lágbára, ẹ ò sì máa wàásù nípa mi. Torí náà, ẹ lọ máa wàásù ní Jerúsálẹ́mù, Jùdíà, Samáríà àtàwọn apá ibi tó jìnnà jù láyé.’

Lẹ́yìn náà, Jésù bẹ̀rẹ̀ sí í gòkè lọ sí ọ̀run títí ìkùukùu fi bò ó. Àwọn ọmọ ẹ̀yìn ẹ̀ wá tẹ́jú mọ́ òkè, àmọ́ wọn ò rí i mọ́.

Àwọn ọmọ ẹ̀yìn náà wá kúrò lórí Òkè Ólífì, wọ́n sì lọ sí Jerúsálẹ́mù. Wọ́n máa ń pàdé pọ̀ déédéé láti gbàdúrà nínú yàrá òkè nílé kan. Wọ́n ń dúró de Jésù kó wá sọ ohun tí wọ́n máa ṣe.

“A ó sì wàásù ìhìn rere Ìjọba yìí ní gbogbo ilẹ̀ ayé tí à ń gbé, kó lè jẹ́ ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.”​—Mátíù 24:14

Ìbéèrè: Àṣẹ wo ni Jésù pa fáwọn ọmọlẹ́yìn ẹ̀? Kí ló ṣẹlẹ̀ lórí Òkè Ólífì?

Mátíù 28:16-20; Lúùkù 24:49-53; Jòhánù 20:30, 31; Ìṣe 1:2-14; 1 Kọ́ríńtì 15:3-6

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́