ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • sjj orin 92
  • Ibi Tá À Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ibi Tá À Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè
  • “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ibi Tá A Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè
    Kọrin sí Jèhófà
  • Jèhófà Ni Ìyìn àti Ògo Yẹ!
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jọ̀ọ́, Gbọ́ Àdúrà Mi
    “Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
  • Jọ̀wọ́ Gbọ́ Àdúrà Mi
    Kọrin sí Jèhófà
Àwọn Míì
“Fi Ayọ̀ Kọrin” sí Jèhófà
sjj orin 92

ORIN 92

Ibi Tá À Ń Fi Orúkọ Rẹ Pè

Bíi Ti Orí Ìwé

(1 Kíróníkà 29:16)

  1. 1. Àǹfààní ńlá lèyí jẹ́ fún wa

    Láti kọ́ ilé yìí fún ọ!

    Gbogbo ohun tá a ní, tìrẹ ni.

    A fi ń buyì fórúkọ rẹ.

    Tọkàntọkàn la ń fi iṣẹ́ wa,

    Okun wa, ohun ìní wa,

    Bọlá fún orúkọ mímọ́ rẹ.

    Ọlọ́run wa, jọ̀ọ́ tẹ́wọ́ gbà á.

    (ÈGBÈ)

    Ilé náà rè é níwájú rẹ,

    Tá ó máa forúkọ rẹ pè.

    A ti yà á sí mímọ́ fún ọ;

    Tìrẹ ni títí láéláé.

  2. 2. Ní báyìí, a gbórúkọ rẹ ga,

    Kógo àtìyìn jẹ́ tìrẹ.

    Kí àwọn tó ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa rẹ

    Máa pọ̀ sí i nínú ilé yìí.

    A ó máa jọ́sìn rẹ nínú ‘lé yìí,

    A ó sì máa tọ́jú rẹ̀ dáadáa.

    Kó lè máa jẹ́rìí fáwọn èèyàn,

    Kó tiṣẹ́ ‘wàásù wa lẹ́yìn.

    (ÈGBÈ)

    Ilé náà rè é níwájú rẹ,

    Tá ó máa forúkọ rẹ pè.

    A ti yà á sí mímọ́ fún ọ;

    Tìrẹ ni títí láéláé.

(Tún wo 1 Ọba 8:18, 27; 1 Kíró. 29:​11-14; Ìṣe 20:24.)

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́