ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w96 3/1 ojú ìwé 3
  • ‘Mo Ha Já Mọ́ Nǹkan Kan Lójú Ọlọrun Bí?’

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • ‘Mo Ha Já Mọ́ Nǹkan Kan Lójú Ọlọrun Bí?’
  • Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ǹjẹ́ “Májẹ̀mú Láéláé” Ṣì Wúlò?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2007
  • Ọjọ́ Tá Ò Gbọ́dọ̀ Gbàgbé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Jòhánù 3:16—“Torí Ọlọ́run Nífẹ̀ẹ́ Ayé Gan-an”
    Àlàyé Àwọn Ẹsẹ Bíbélì
  • Fílípì—Ajíhìnrere Tó Nítara
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
Àwọn Míì
Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
w96 3/1 ojú ìwé 3

‘Mo Ha Já Mọ́ Nǹkan Kan Lójú Ọlọrun Bí?’

“MO HA Já Mọ́ Nǹkan Kan Bí? Ọlọrun Ha Bìkítà Bí?” Báyìí ni àkọlé ọ̀rọ̀ àpilẹ̀kọ kan tí ó jẹyọ nínú ìwé ìròyìn Christianity Today ṣe kà. Philip Yancey, tí ó kọ ọ̀rọ̀ àpilẹ̀kọ náà, sọ pé: “Ìṣòro ìrora ni kókó ọ̀rọ̀ ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àgbéṣe mi gẹ́gẹ́ bí òǹkọ̀wé. Mo máa ń padà nígbà gbogbo sórí ìbéèrè kan náà, bí ẹni ń dẹ egbò tí kò tí ì jiná tán. Mo máa ń gbọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn òǹkàwé mi, àwọn làásìgbò ìtàn wọn sì máa ń fìdí iyè méjì mi múlẹ̀.”

Bóyá ìwọ pẹ̀lú ti ṣe kàyéfì nípa ọkàn-ìfẹ́ Ọlọrun nínú ìgbésí ayé rẹ. O lè mọ Johannu 3:16 dáradára, tí ó sọ pé “Ọlọrun nífẹ̀ẹ́ ayé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́ tí ó fi fi Ọmọkùnrin bíbí rẹ̀ kanṣoṣo fúnni.” Tàbí o lè ti ka Matteu 20:28, tí ó sọ pé Jesu wá láti “fi ọkàn rẹ̀ fúnni gẹ́gẹ́ bí ìràpadà kan ní pàṣípààrọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn.” Síbẹ̀ o lè béèrè pé, ‘Ọlọrun ha kà mí sí bí? Ó ha bìkítà nípa mi gẹ́gẹ́ bí ẹnì kan bí?’ Ìdí rere wà láti gbà gbọ́ pé ó ṣe bẹ́ẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a óò ti rí i.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́