ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w04 9/15 ojú ìwé 3-4
  • “Ẹ Máa Gbàdúrà ní Ọ̀nà Yìí”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • “Ẹ Máa Gbàdúrà ní Ọ̀nà Yìí”
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé Àdúrà Olúwa Ni Àdúrà Tó Dáa Jù Láti Gbà?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Ohun Tó Yẹ Kó O Mọ̀ Nípa Àdúrà Olúwa
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
  • Ẹ Máa Gbé Ọwọ́ Ìdúróṣinṣin Sókè Nínú Àdúrà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
  • Ẹ Duro Pẹkipẹki Ti Jehofa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2004
w04 9/15 ojú ìwé 3-4

“Ẹ Máa Gbàdúrà ní Ọ̀nà Yìí”

ǸJẸ́ o mọ Àdúrà Olúwa? Àdúrà àfiṣàpẹẹrẹ tí Jésù Kristi kọ́ni là ń pè bẹ́ẹ̀. Nígbà tí Jésù ń ṣe ohun tọ́pọ̀ èèyàn mọ̀ sí Ìwàásù Lórí Òkè, ó sọ pé: “Nítorí náà, kí ẹ máa gbàdúrà ní ọ̀nà yìí.” (Mátíù 6:9) Níwọ̀n bó ti jẹ́ pé Jésù ló fi àdúrà náà lélẹ̀, wọ́n sábà máa ń pè é ní Àdúrà Olúwa, a sì tún mọ̀ ọ́n sí Baba Wa Tí Ń Bẹ Lọ́run.—Paternoster ní èdè Látìn.

Ọ̀pọ̀ èèyàn yíká ayé ló mọ Àdúrà Olúwa sórí wọ́n sì máa ń kà á lákàtúnkà, kódà ojoojúmọ́ làwọn kan ń kà á. Ọ̀pọ̀ ló ti ka àdúrà yìí sókè ketekete níléèwé àti níbi àwọn ayẹyẹ ìsìn. Kí ló mú káwọn èèyàn ka Àdúrà Olúwa sí tó bẹ́ẹ̀?

Cyprian tó ń kọ́ àwọn èèyàn lẹ́kọ̀ọ́ ìsìn ní ọ̀rúndún kẹta kọ̀wé pé: “Àdúrà wo ló tún lè múni sún mọ́ Ọlọ́run ju èyí tí Jésù kọ́ni lọ . . . ? Àdúrà wo sí Baba ló tún lè jóòótọ́ ju èyí tí Ọmọ, tóun fúnra rẹ̀ jẹ́ Òtítọ́, fi lé wa lọ́wọ́?”—Jòhánù 14:6.

Ìwé Katikísìmù Ìjọ Kátólíìkì sọ pé Baba Wa Tí Ń Bẹ Lọ́run jẹ́ àdúrà tó “ṣe kókó fáwọn Kristẹni.” Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ The World Book Encyclopedia pàápàá gbà pé àdúrà yìí ṣe pàtàkì púpọ̀ fún gbogbo àwọn oníṣọ́ọ̀ṣì, ó sì pè é ní ọ̀kan pàtàkì lára “àwọn gbólóhùn tí kò ṣe é fọwọ́ rọ́ sẹ́yìn nínú ẹ̀sìn Kristẹni.”

Síbẹ̀, a ò gbọ́dọ̀ gbójú fo kókó náà dá pé, ọ̀pọ̀ àwọn tó ń ka Àdúrà Olúwa ni kò fi bẹ́ẹ̀ mọ ìtumọ̀ àdúrà náà. Ìwé ìròyìn Ottawa Citizen tó ń jáde lórílẹ̀-èdè Kánádà sọ pé: “Bó o bá jẹ́ ẹni tó máa ń lọ sí Ṣọ́ọ̀ṣì tàbí tó o ti lọ rí, ó ṣeé ṣe kó o lè ka Àdúrà Olúwa lólówuuru, àmọ́ tó bá di pé kó o fara balẹ̀ kà á kó sì yé ọ, ó lè ṣòro fún ọ.”

Ǹjẹ́ ó tiẹ̀ ṣe pàtàkì ká lóye àdúrà tí à ń gbà sí Ọlọ́run? Kí nìdí tí Jésù fi kọ́ wa ní Àdúrà Olúwa? Kí lo lè rí kọ́ nínú rẹ̀? Ó yá, jẹ́ ká gbé àwọn ìbéèrè wọ̀nyí yẹ̀ wò.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́