ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp17 No. 1 ojú ìwé 5-6
  • Báwo Ni Mo Ṣe Máa Gbádùn Ẹ̀?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Ni Mo Ṣe Máa Gbádùn Ẹ̀?
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Orí àti Ẹsẹ—Ta Ló Fi Wọ́n Sínú Bíbélì?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2016
  • Jíjàǹfààní Láti Inú Bibeli Kíkà Lójoojúmọ́
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1995
  • Ohun Tó O Lè Fi Kẹ́kọ̀ọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Bó O Ṣe Lè Jàǹfààní Púpọ̀ Látinú Bíbélì
    Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìjíròrò Látinú Bíbélì
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2017
wp17 No. 1 ojú ìwé 5-6
Obìnrin kan ń lo ohun tó lè fi kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì nígbà tó ń ka Bíbélì

KÓKÓ IWÁJÚ ÌWÉ | BÓ O ṢE LÈ RÍ Ẹ̀KỌ́ KỌ́ LÁTINÚ KÍKA BÍBÉLÌ

Báwo Ni Mo Ṣe Máa Gbádùn Ẹ̀?

Ṣé kíka Bíbélì máa ń gbádùn mọ́ni? Àǹfààní wo lo sì máa rí níbẹ̀? Ìdáhùn àwọn ìbéèrè yìí sinmi lórí ọ̀nà tí ò ń gbà ka Bíbélì. Jẹ́ ká wo ohun tó o lè ṣe láti mú kí Bíbélì máa wù ẹ́ kà, kó o sì gbádùn rẹ̀.

Lo Bíbélì tó dáa, tí ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ sì bágbà mu. Tó o bá ka Bíbélì tí àwọn ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ ṣòro láti lóye tàbí tí kò bágbà mu, oò ní gbádùn ohun tí ò ń kà nínú rẹ̀. Torí náà, Bíbélì tó máa tètè yé ẹ táwọn ọ̀rọ̀ inú rẹ̀ sì máa wọ̀ ẹ́ lọ́kàn ni kó o lò. Lẹ́sẹ̀ kan náà, ó gbọ́dọ̀ jẹ́ Bíbélì tí wọ́n fara balẹ̀ túmọ̀, tí ìtúmọ̀ rẹ̀ sì péye.a

Lo ohun èlò ìgbàlódé. Lóde òní, kì í ṣe orí ìwé nìkan la ti lè rí Bíbélì kà, a tún lè wà á jáde sórí fóònù, tablet tàbí kọ̀ǹpútà, ká sì máa kà á látibẹ̀. Àwọn Bíbélì orí ẹ̀rọ kan tiẹ̀ wà tó tún máa fún ẹ láǹfààní láti wo ẹsẹ Bíbélì kan tàbí kókó ọ̀rọ̀ kan nínú àwọn ìtúmọ̀ Bíbélì míì kó o lè fi wọ́n wéra. Tó bá jẹ́ pé èyí tó o lè tẹ́tí sí ló rọ̀ ẹ́ lọ́rùn, Bíbélì tí wọ́n ti kà sílẹ̀ tún wà tó o lè máa gbọ́. Ọ̀pọ̀ èèyàn gbádùn kí wọ́n máa tẹ́tí sí Bíbélì tí wọ́n ti kà sílẹ̀ nígbà tí wọ́n bá wà nínú mọ́tò, tí wọ́n ń fọṣọ, tàbí tí wọ́n ń ṣe àwọn nǹkan míì tó gbà wọ́n láyè láti máa fetí sílẹ̀. Oò ṣe gbìyànjú èyí tó máa rọrùn fún ẹ nínú àwọn àbá yìí?

Lo ohun tó o lè fi kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Àwọn ohun tó o lè fi kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì yìí máa jẹ́ kó o túbọ̀ jàǹfààní nínú kíka Bíbélì. O lè lo àwòrán àwọn ilẹ̀ tí wọ́n dárúkọ nínú Bíbélì, èyí máa jẹ́ kó o rí àwọn ibi tí Bíbélì mẹ́nu kàn, wàá sì lè fọkàn yàwòrán ohun tó ṣẹlẹ̀ níbẹ̀. Àwọn àpilẹ̀kọ bí èyí tó wà nínú ìwé ìròyìn yìí tàbí àwọn tó wà ní apá tá a pè ní “Ẹ̀kọ́ Bíbélì” lórí ìkànnì jw.org, máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti mọ ohun tí àwọn apá kan nínú Bíbélì túmọ̀ sí.

Lo onírúurú ọ̀nà. Tí kíka Bíbélì láti páálí dé páálí bá jọ pé ó kà ẹ́ láyà, o lè bẹ̀rẹ̀ nípa kíka àwọn apá tó gbádùn mọ́ ẹ jù lọ. Tó o bá fẹ́ mọ ìtàn àwọn èèyàn tó lókìkí nínú Bíbélì, o lè ka àwọn apá Bíbélì tó dá lórí ìtàn àwọn èèyàn. A sọ ọ̀nà kan tó o lè gbà ṣe é nínú àpótí tó wà nínú àpilẹ̀kọ yìí, ìyẹn àpótí tí àkòrí rẹ̀ jẹ́ “Mọ Àwọn Èèyàn Tí Bíbélì Sọ̀rọ̀ Nípa Wọn.” O sì tún lè ka onírúurú ìtàn tó wà nínú Bíbélì tàbí bí wọ́n ṣe ṣẹlẹ̀ tẹ̀ léra. Oò ṣe gbìyànjú ọ̀kan lára àwọn àbá náà?

a Ọ̀pọ̀ ti rí i pé Bíbélì Ìwé Mímọ́ ní Ìtumọ̀ Ayé Tuntun péye, ó ṣeé gbára lé, ó sì rọrùn láti kà. Àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà la tẹ Bíbélì yìí, ó sì wà ní èdè tó lé ní àádóje [130]. O lè wa Bíbélì yìí jáde lórí ìkànnì wa, ìyẹn jw.org/yo tàbí kó o wa JW Library jáde láti play store sorí fóònù rẹ. Tó o bá sì fẹ́, ọ̀kan lára àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà lè mú èyí tá a tẹ̀ jáde wá fún ẹ nílé.

MỌ ÀWỌN ÈÈYÀN TÍ BÍBÉLÌ SỌ̀RỌ̀ NÍPA WỌN

Díẹ̀ lára àwọn obìnrin olóòótọ́

Ábígẹ́lì

1 Sámúẹ́lì orí 25

Ẹ́sítérì

Ẹ́sítérì orí 2-5, 7-9

Hánà

1 Sámúẹ́lì orí 1-2

Màríà

(ìyá Jésù) Mátíù orí 1-2; Lúùkù orí 1-2; tún wo Jòhánù 2:​1-12; Ìṣe 1:​12-14; 2:​1-4

Ráhábù

Jóṣúà orí 2, 6; tún wo Hébérù 11:​30, 31; Jákọ́bù 2:​24-26

Rèbékà

Jẹ́nẹ́sísì orí 24-27

Sárà

Jẹ́nẹ́sísì orí 17-18, 20-21, 23; tún wo Hébérù 11:11; 1 Pétérù 3:​1-6

Díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin tó tayọ

Ábúráhámù

Jẹ́nẹ́sísì orí 11-24; tún wo orí 25:​1-11

Dáfídì

1 Sámúẹ́lì orí 16-30; 2 Sámúẹ́lì orí 1-24; 1 Àwọn Ọba orí 1-2

Jésù

Ìwé Ìhìn Rere Mátíù, Máàkù, Lúùkù, àti Jòhánù

Mósè

Ẹ́kísódù orí 2-20, 24, 32-34; Númérì orí 11-17, 20, 21, 27, 31; Diutarónómì orí 34

Nóà

Jẹ́nẹ́sísì orí 5-9

Pọ́ọ̀lù

Ìṣe orí 7-9, 13-28

Pétérù

Mátíù orí 4, 10, 14, 16-17, 26; Ìṣe orí 1-5, 8-12

ÀWỌN OHUN ÈLÒ ÌKẸ́KỌ̀Ọ́ BÍBÉLÌ TÁWA ẸLẸ́RÌÍ JÈHÓFÀ ṢE

  • JW.ORG​—Ìkànnì yìí ní ọ̀pọ̀ ohun èlò téèyàn lè fi kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì, irú bí apá tá a pè ní “Ohun Tí Bíbélì Sọ.” Ó tún ní ìtọ́ni lórí bá a ṣe lè wa ètò ìṣiṣẹ́ JW Library jáde

  • Wo Ilẹ̀ Dáradára Náà​—Ìwé pẹlẹbẹ yìí ní àwọn àwòrán ilẹ̀ tí Bíbélì mẹ́nu kàn

  • Insight on the Scriptures (Gẹ̀ẹ́sì)​—Ìwé gbédègbẹ́yọ̀ yìí ní ìdìpọ̀ méjì, ó sì ṣe àlàyé nípa àwọn èèyàn, ilẹ̀ àtàwọn nǹkan míì tí Bíbélì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀

  • “All Scripture Is Inspired of God and Beneficial” (Gẹ̀ẹ́sì)​—Ìwé yìí sọ nípa ìgbà tí wọ́n kọ àwọn ìwé inú Bíbélì, ibi tí wọ́n ti kọ ọ́ àti ìdí tí wọ́n fi kọ ọ́, ó sì ṣe àlàyé ṣókí nípa ìwé Bíbélì kọ̀ọ̀kan

  • The Bible​—God’s Word or Man’s? (Gẹ̀ẹ́sì)​—Ìwé kékeré yìí ní àwọn ìwádìí tá a fẹ̀sọ̀ ṣe nípa àwọn ẹ̀rí tó fi hàn pé Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ni Bíbélì

  • Kí Ló Wà Nínú Bíbélì?​—Ìwé pẹlẹbẹ olójú ìwé 32 yìí ṣe àkópọ̀ ṣókí nípa ohun tó wà nínú Bíbélì

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́