ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 8/00 ojú ìwé 7
  • Máa Fúnrúgbìn ní Yanturu, Ṣùgbọ́n Lo Ìfòyemọ̀

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Fúnrúgbìn ní Yanturu, Ṣùgbọ́n Lo Ìfòyemọ̀
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Lo Àwọn Ìwé Wa Lọ́nà Ọgbọ́n
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Ètò Mímú Kí Ìpínkiri Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Rọrùn Tí A Ṣe
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2001
  • Bí A Ṣe Ń Rí Owó Bójú Tó Iṣẹ́ Ìjọba Ọlọ́run
    Ìjọba Ọlọ́run Ti Ń Ṣàkóso!
  • Máa Fi Ìmọrírì Àtọkànwá Hàn fún Àwọn Ìwé Ìkẹ́kọ̀ọ́ Wa
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
km 8/00 ojú ìwé 7

Máa Fúnrúgbìn ní Yanturu, Ṣùgbọ́n Lo Ìfòyemọ̀

1 Kò sí àgbẹ̀ tí kò mọ̀ pé bí òun bá fúnrúgbìn ní yanturu, òun á kórè ní yanturu bí nǹkan kò bá yíwọ́, ṣùgbọ́n bí òun bá fúnrúgbìn kín-ún, ó ti dájú pé kín-ún náà lòun máa kórè. (2 Kọ́r. 9:6) Àwọn àgbẹ̀ máa ń ṣọ́ra ni kí wọ́n má bàa gbin nǹkan síbi tí kò ti ní lè dàgbà. A nílò ìfòyemọ̀ bí èyí nígbà tí a bá ń fi ìwé wa lọ àwọn èèyàn lóde ẹ̀rí. Ohun tí a fẹ́ ni pé àwọn tó fẹ́ láti ka ìwé wa ni a fẹ́ fi wọ́n lé lọ́wọ́. A fẹ́ kí àwọn tó jẹ́ ẹni yíyẹ ní àǹfààní láti kẹ́kọ̀ọ́ nípa inú rere àìlẹ́tọ̀ọ́sí Jèhófà àti ìrètí Ìjọba náà.

2 Ǹjẹ́ o rí i pé àwọn ìwé ìròyìn, ìwé pẹlẹbẹ, àti àwọn ìtẹ̀jáde mìíràn ń ṣẹ́jọ sínú àpótí ìwé ní ilé rẹ nígbà tó jẹ́ pé o ṣì lè lò wọ́n láti jẹ́ kí àwọn ẹni yíyẹ tó wà ní ìpínlẹ̀ rẹ ní ìmọ̀ òtítọ́? (Fi wé Mátíù 25:25.) Ǹjẹ́ o máa ń fà sẹ́yìn lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan láti fi ìwé ìròyìn àti àwọn ìwé wa mìíràn lọ àwọn èèyàn nígbà tí o bá dé ọ̀dọ̀ wọn fún ìgbà àkọ́kọ́ kìkì nítorí pé o rí i pé kò rọrùn fún ọ láti sọ nípa bí a ti ń ṣe ìtìlẹ́yìn fún iṣẹ́ ìwàásù Ìjọba náà? Àwọn akéde onírìírí ti rí i pé àwọn onílé tí wọ́n mọrírì máa ń ṣètìlẹyìn nígbà tí a bá sọ fún wọn ní tààràtà nípa bí a ṣe ń lo ọrẹ tí wọ́n bá fi ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ Ìjọba náà, tí a sì sọ ọ́ ní ṣókí.

3 O lè sọ pé:

◼ “O lè máa ṣe kàyéfì nípa bí a ṣe lè máa fún àwọn èèyàn ní ìwé láìjẹ́ pé a béèrè iye kan ní pàtó. Ó jẹ́ ara iṣẹ́ ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ jákèjádò ayé tí a máa ń fi ọrẹ àtinúwá ṣètìlẹ́yìn fún. Bí o bá fẹ́ láti fi ọrẹ díẹ̀ ṣètìlẹ́yìn fún iṣẹ́ yìí, inú mi yóò dùn gidigidi láti gbà á.”

4 Ọ̀pọ̀ onílé ló máa ń béèrè iye owó ìwé wa.

O lè fèsì pé:

◼ “A kì í dá iye lé ìwé wa nítorí ọrẹ àtinúwá la máa fi ń ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ wa. Bí o bá fẹ́ láti fi ọrẹ díẹ̀ ṣètìlẹyìn lónìí, inú wa yóò dùn, a óò sì lò ó fún iṣẹ́ ìwàásù tí a ń ṣe jákèjádò ayé.”

Tàbí o lè sọ pé:

◼ “A máa ń fún gbogbo àwọn tó bá fẹ́ láti túbọ̀ kẹ́kọ̀ọ́ nípa Bíbélì ní ìwé wa. Bí o bá fẹ́ láti fi ọrẹ díẹ̀ ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ tí a ń ṣe jákèjádò ayé yìí, inú mi yóò dùn láti bá ọ fi ọrẹ náà ránṣẹ́.”

5 Lẹ́nu iṣẹ́ ìwé ìròyìn, àwọn akéde kan máa ń ṣí ìwé ìròyìn náà wọ́n á sì fi han onílé níbi tí a kọ ọ́ sí pé:

◼ “Bí o ṣe rí i níhìn-ín, ọrẹ àtinúwá ni a fi ń ṣètìlẹyìn fún iṣẹ́ wa. Bí o bá fẹ́ láti fi ọrẹ díẹ̀ ṣèrànwọ́ fún iṣẹ́ yìí, mo lè gbà á.”

Tún wo gbólóhùn mìíràn tí o lè sọ ní ṣókí:

◼ “Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a kì í dá iye lé ìwé wa, a máa ń gba ọrẹ tó mọ níwọ̀n fún iṣẹ́ tí a ń ṣe jákèjádò ayé yìí.”

6 Kí a má ṣe fà sẹ́yìn nínú fífúnrúgbìn Ìjọba náà nítorí pé a ń lọ́tìkọ̀ láti sọ bí a ṣe ń gbọ́ bùkátà iṣẹ́ yìí. Lọ́wọ́ kan náà, a nílò ìfòyemọ̀ kí a má bàa fi àwọn ìwé wa ṣòfò sórí ‘ilẹ̀ àpáta.’ (Máàkù 4:5, 6, 16, 17) Inú àwọn tó mọrírì ìhìn rere tí a ń mú tọ̀ wọ́n lọ máa ń dùn pé àwọn ní àǹfààní láti fi ohun ìní àwọn tì í lẹ́yìn.—Fi wé Mátíù 10:42.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́