ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 4/99 ojú ìwé 7
  • Ìpinnu Wa—Láti Máa Rìn ní Ọ̀nà Ìgbésí Ayé Tí Jèhófà Fẹ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìpinnu Wa—Láti Máa Rìn ní Ọ̀nà Ìgbésí Ayé Tí Jèhófà Fẹ́
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Rìn Ní Ọ̀nà Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1999
  • Ẹ Wà Lójúfò, Kí Ẹ sì Máa Tẹ̀ Síwájú Láìfòyà!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2002
  • Ǹjẹ́ O Ń Ṣe Ara Rẹ Láǹfààní?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2000
  • Ìmọ̀ Ẹ̀kọ́—Lò Ó Láti Yin Jehofa
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1996
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
km 4/99 ojú ìwé 7

Ìpinnu Wa—Láti Máa Rìn ní Ọ̀nà Ìgbésí Ayé Tí Jèhófà Fẹ́

1 Ọ̀kan lára ohun tí ó ṣe pàtàkì jù lọ ní Àpéjọpọ̀ “Ọ̀nà Ìgbésí Ayé Tí Ọlọ́run Fẹ́” ni ìpinnu tí a ṣe nínú ọ̀rọ̀ àsọyé tí ó kẹ́yìn. Ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ìpolongo yìí: “Àwa . . . fi tọkàntọkàn gbà pé ọ̀nà Ọlọ́run ni ọ̀nà ìgbésí ayé tí ó dára jù lọ.” Rántí àwọn kókó pàtàkì mélòó kan nínú ìpinnu náà tí gbogbo wa dáhùn sí pé, “BẸ́Ẹ̀ NI!”

2 Ìpinnu wa ni pé a óò máa jẹ́ mímọ́ lójú Jèhófà, láìlábààwọ́n nínú ayé. A óò máa bá a lọ láti fi ìfẹ́ Ọlọ́run ṣáájú nínú ìgbésí ayé wa. Bí a ti ń lo Bíbélì, Ọ̀rọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí amọ̀nà, a kò ní yà sí ọ̀tún tàbí sí òsì, a óò sì tipa báyìí jẹ́rìí sí i pé ọ̀nà Ọlọ́run dára gan-an ju ọ̀nà ayé lọ.

3 Ayé lápapọ̀ kò ka ọ̀nà ìgbésí ayé tí Ọlọ́run fẹ́ sí, wọ́n sì ń rí àbájáde rẹ̀. (Jer. 10:23) Nítorí náà, a gbọ́dọ̀ máa bá a lọ láti jẹ́ ẹni tí Jèhófà, Atóbilọ́lá Olùfúnninítọ̀ọ́ni wa, ń kọ́ lẹ́kọ̀ọ́, ẹni tó sọ pé: “Èyí ni ọ̀nà. Ẹ máa rìn nínú rẹ̀.” (Aísá. 30:21) Gẹ́gẹ́ bí a ti fi hàn nínú Ìwé Mímọ́, ọ̀nà ìgbésí ayé tí Jèhófà fẹ́ ni ó dára jù lọ ní gbogbo ọ̀nà. Láti lè máa rìn ní ọ̀nà yẹn, ó pọndandan pé ká lo àǹfààní gbogbo ohun tí Jèhófà ń kọ́ wa.

4 Ìtòlẹ́sẹẹsẹ Ìkọ́nilẹ́kọ̀ọ́ Tí Ó Dára Jù Lọ Tí Ó Jẹ́ ti Jèhófà: Jèhófà ń kọ́ wa ni ohun tó jẹ́ ète gidi nínú ìgbésí ayé àti bí a ṣe lè lo ìwàláàyè wa lọ́nà tó dára jù lọ. Ó ń kọ́ wa báa ṣe lè mú kí ìgbésí ayé wa sunwọ̀n sí i ní ti èrò orí, ní ti ìwà híhù, àti nípa tẹ̀mí. Ó ń kọ́ wa báa ṣe lè máa gbé ní àlàáfíà pẹ̀lú àwọn arákùnrin wa, pẹ̀lú àwọn ìdílé wa, àti pẹ̀lú ènìyàn ẹlẹgbẹ́ wa. Ó ń ṣe èyí nípasẹ̀ ìwé rẹ̀, Bíbélì, àti nípasẹ̀ ètò rẹ̀.

5 Àwọn ìpàdé ìjọ wa ṣe pàtàkì nínú èyí. Bí a ṣe ń lọ sí gbogbo ìpàdé márààrún déédéé táa sì ń kópa nínú wọn, a ń gba ìdálẹ́kọ̀ọ́ kíkúnrẹ́rẹ́ gẹ́gẹ́ bí òjíṣẹ́ ìhìn rere, a sì ń gba ìmọ̀ ẹ̀kọ́ tó kúnjú òṣùwọ̀n nínú ìgbésí ayé Kristẹni. (2 Tím. 3:16, 17) Atóbilọ́lá Olùfúnninítọ̀ọ́ni wa tún ń pèsè ẹ̀kọ́ ìṣàkóso Ọlọ́run síwájú sí i nípasẹ̀ àwọn àpéjọ àti àpéjọpọ̀. Ohun tí ó yẹ kí ó jẹ́ góńgó wa ni pé a kì yóò pàdánù ìpàdé kan tàbí ìtòlẹ́sẹẹsẹ kan bí ìlera àti àwọn àyíká ipò wa bá gbà wá láyè.

6 Ǹjẹ́ kí a máa fi aápọn bá a nìṣó ní àwọn ọjọ́ tí ń bẹ níwájú ní rírìn ní ọ̀nà ìgbésí ayé tí Ọlọ́run ń fẹ́, sí ìyìn Jèhófà àti àǹfààní àìnípẹ̀kun wa!—Aísá. 48:17.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́