ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 2/99 ojú ìwé 4
  • Fi Ìwé Ayọ̀ Ìdílé Lọ Tàgbàtèwe

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Fi Ìwé Ayọ̀ Ìdílé Lọ Tàgbàtèwe
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ríran Àwọn Ìdílé Lọ́wọ́ Láti Ní Ọjọ́ Ọ̀la Wíwà Pẹ́ Títí
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Ṣíṣàjọpín Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé Pẹ̀lú Àwọn Ẹlòmíràn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
  • Àwọn Ìnasẹ̀ Ọ̀rọ̀ Tí A Dábàá fún Lílò Nínú Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Pápá
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2002
  • Ìmọ̀ Láti Ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Ń Dáhùn Ọ̀pọ̀ Ìbéèrè
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1997
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—1999
km 2/99 ojú ìwé 4

Fi Ìwé Ayọ̀ Ìdílé Lọ Tàgbàtèwe

1 Ọmọdékùnrin ọlọ́dún mọ́kànlá kan láti California fi ìmọrírì rẹ̀ hàn fún ìwé náà, Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé. Ó kọ̀wé pé: “Mo kún fún ìmoore nítorí rẹ̀, mo sì ń fún àwọn ìdílé yòókù níṣìírí láti ka ìwé yìí nítorí ó tayọ lọ́lá. Ó . . . ń ran ìdílé mi lọ́wọ́ láti rí àlàáfíà àti ayọ̀ nínú ilé wa.” Ó yẹ kí ìrírí èwe yìí fún wa níṣìírí láti fi ìwé Ayọ̀ Ìdílé lọ tàgbàtèwe. Àwọn àbá kan nìyí tí ó ṣeé ṣe kí o fẹ́ láti gbìyànjú wò nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ ní oṣù February.

2 Bí o bá bá ọ̀dọ́ kan pàdé, o lè sọ pé:

◼ “Ọ̀pọ̀ ọ̀dọ́ ń ronú nípa ìgbéyàwó. Ṣùgbọ́n nígbà tí a bi wọ́n bóyá wọ́n ṣe tán láti ṣègbéyàwó tàbí wọn kò ṣe tán, ọ̀pọ̀ sọ pé kò dá àwọn lójú. Jẹ́ kí ń fi ohun tí ìwé àmúléwọ́ yìí sọ nípa kókó ẹ̀kọ́ yìí hàn ọ́.” Ṣí ìwé Ayọ̀ Ìdílé sí ojú ìwé 14, kí o sì ka ìpínrọ̀ 3. Lẹ́yìn náà, tọ́ka sí ìsọ̀rí orí ọ̀rọ̀ kọ̀ọ̀kan nínú orí náà. Fi ìwé náà lọ̀ ọ́ ní iye tí a máa ń fi í sóde, kí o sì ṣètò láti padà lọ.

3 Nígbà tí o bá ń bá òbí kan sọ̀rọ̀, o lè sọ pé:

◼ “A ń bá àwọn òbí ṣàjọpín àwọn ìlànà gbígbéṣẹ́ tí ó wúlò ní ti gidi nínú títọ́ àwọn ọmọ. A ti ṣàkójọ ìwọ̀nyí sínú ìwé àmúléwọ́ yìí, Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé.” Ṣí ìwé náà sí ojú ìwé 55. Ka ìpínrọ̀ 10, lẹ́yìn náà ka Diutarónómì 6:6, 7, tí ó wà ní ìpínrọ̀ 11. Lẹ́yìn náà, tọ́ka sí àwọn gbólóhùn tí a fi àwọn lẹ́tà wínníwínní kọ ní ìpínrọ̀ 12 sí 16. Máa bá ọ̀rọ̀ rẹ lọ nípa sísọ pé: “Ìwé yìí ti ran ọ̀pọ̀ lọ́wọ́ láti ṣàṣeyọrí gidigidi gẹ́gẹ́ bí òbí. Bí o bá fẹ́ láti kà á, inú mi yóò dùn láti fi ẹ̀dà yìí sílẹ̀ fún ọ ní ọrẹ ₦55 (ẹlẹ́yìn rírọ̀, ₦50).”

4 Bí o bá ń bá àgbàlagbà sọ̀rọ̀, o lè sọ pé:

◼ “Nígbà tí mo bá ka àlàyé kúkúrú yìí tán, kí ẹ jọ̀wọ́ sọ èrò yín fún mi.” Ṣí ìwé Ayọ̀ Ìdílé sí ojú ìwé 169 kí o sì ka gbólóhùn méjì àkọ́kọ́ ní ìpínrọ̀ 17. Lẹ́yìn náà, sọ pé kí ó fèsì. Lójú ìwòye ohun tí ó bá jẹ́ èsì rẹ̀, o lè túbọ̀ ṣàyọkà láti inú ìwé náà kí o tó fi lọ̀ ọ́.

5 Nígbà tí o bá ń padà ṣiṣẹ́ lórí ìwé Ayọ̀ Ìdílé tí o fi sóde, fi í sọ́kàn pé o fẹ́ bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì. Ó lè bẹ̀rẹ̀ ní Ẹ̀kọ́ 8 nínú ìwé pẹlẹbẹ Béèrè tàbí orí 15 nínú ìwé Ìmọ̀. Ní àkókò yìí, ẹ jẹ́ kí a sakun láti ran tàgbàtèwe lọ́wọ́ láti máa gbé ìgbésí ayé ìdílé Kristẹni tí ó láyọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́