ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 3/03 ojú ìwé 8
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
  • Ohun Tó O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2006
  • Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2005
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2003
km 3/03 ojú ìwé 8

Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn

Ilé Ìṣọ́ Mar. 15

“Ǹjẹ́ o rò pé àwọn ẹ̀kọ́ tí Jésù fi kọ́ni wúlò lóde òní? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Ó dájú pé o fara mọ́ àṣẹ yìí, èyí tí Jésù pa ní ọjọ́ tó lò kẹ́yìn ṣáájú kó tó kú. [Ka Jòhánù 15:12.] Jésù tún kọ́ni láwọn ẹ̀kọ́ mìíràn tó ṣeyebíye lọ́jọ́ náà. Ìtẹ̀jáde Ilé Ìṣọ́ yìí fi hàn bí a ṣe lè jàǹfààní nínú wọn.”

Ilé Ìṣọ́ Apr. 1

“Àwòrán ayẹyẹ tí gbogbo èèyàn mọ̀ sí Oúnjẹ Alẹ́ Olúwa lò ń wò níbí yìí. [Fi iwájú àti ẹ̀yìn ìwé ìròyìn náà han onílé.] Ǹjẹ́ o mọ̀ pé òun nìkan ni ayẹyẹ tí Bíbélì pa láṣẹ fún àwọn Kristẹni pe kí wọ́n máa ṣèrántí rẹ̀? [Jẹ́ kí ó fèsì. Lẹ́yìn náà ka Lúùkù 22:19.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé ohun tó mú kí ayẹyẹ yìí ṣe pàtàkì tó bẹ́ẹ̀ àti bó ṣe kàn ọ́.”

Jí! Apr. 8

“Ǹjẹ́ o ti ṣàkíyèsí pé lónìí, ọ̀pọ̀ èèyàn ló máa ń ṣòro fún láti rí oorun tó tó sùn? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Àníyàn tàbí ìdààmú ọkàn lè wà lára ohun tó ń fa èyí. [Ka Oníwàásù 5:12.] Ìwé ìròyìn yìí gbé díẹ̀ lára àwọn ohun tó máa ń fa àìróorunsùn yẹ̀ wò, ó sì fúnni láwọn àbá tó wúlò nípa bí a ṣe lè máa rí oorun sùn dáadáa.”

“Ǹjẹ́ kì í ṣe ohun tó ń bani nínú jẹ́ ni pé oògùn olóró ti ba ayé ọ̀pọ̀ ọ̀dọ́ jẹ́? [Jẹ́ kí ó fèsì.] Lọ́pọ̀ ìgbà, ibi tí ìṣòro náà ti máa ń bẹ̀rẹ̀ ni nígbà táwọn ọ̀dọ́ bá bẹ̀rẹ̀ sí í bá ẹgbẹ́kẹ́gbẹ́ rìn. [Ka 1 Kọ́ríńtì 15:33.] Ìtẹ̀jáde Jí! yìí ṣàgbéyẹ̀wò àwọn ohun tó máa ń sún àwọn ọ̀dọ́ sí bíbẹ̀rẹ̀ sí í lo oògùn olóró àti ohun tí àwọn òbí lè ṣe láti dáàbò bo àwọn ọmọ wọn.”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́