Ohun Tí O Lè Sọ Nípa Àwọn Ìwé Ìròyìn
Ile Iṣọ Apr. 15
“Ǹjẹ́ kò dà bíi pé ẹ̀kọ́ kíkọ́ ò lópin láyé òde òní? [Jẹ́ kó fèsì.] Àmọ́, kò sóhun tó wúlò tó ohun tí ẹsẹ Bíbélì yìí sọ. [Ka Jòhánù 17:3.] Ìwé ìròyìn yìí sọ ohun tí gbólóhùn náà, ‘ìyè àìnípẹ̀kun’ túmọ̀ sí àti béèyàn ṣe lè ní ìmọ̀ tó máa jẹ́ kéèyàn ní ìyè àìnípẹ̀kun.”
Ile Iṣọ May 1
“Nígbà téèyàn wa bá kú, ohun tó máa ń wu àwa ẹ̀dá èèyàn ni pé ká tún padà rí onítọ̀hún. Àbí bẹ́ẹ̀ kọ́? [Jẹ́ kó fèsì.] Ọ̀pọ̀ èèyàn ni ìlérí tó wà nínú Bíbélì pé àwọn òkú yóò jíǹde ti tù nínú. [Ka Jòhánù 5:28, 29.] Ìwé ìròyìn yìí sọ ìgbà tí àjíǹde yóò wáyé àti àwọn tí àjíǹde máa ṣe láǹfààní.”
Jí May 8
“Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fẹ́rẹ̀ẹ́ máà sẹ́ni táwọn èèyàn mọ̀ nípa rẹ̀ tó Jésù Kristi nínú gbogbo àwọn tó ti gbé ayé rí, síbẹ̀, ọ̀pọ̀ èèyàn ló ń ṣe kàyéfì nípa ẹni tí Jésù jẹ́ gan-an. Ǹjẹ́ o mọ̀ pé àwọn àpọ́sítélì Jésù pàápàá ṣe kàyéfì bẹ́ẹ̀? [Jẹ́ kó fèsì, lẹ́yìn náà ka Máàkù 4:41.] Ìwé ìròyìn yìí ṣe àlàyé nípa ẹni tí Jésù jẹ́ gan-an.”
“Ọ̀pọ̀ òbí ló máa ń fòye yan irú fíìmù tí wọ́n fàyè gba àwọn ọmọ wọn láti máa wò. Ǹjẹ́ ó máa ń ṣòro fún ọ láti mọ irú fíìmù tó bójú mu pé kí ìdílé rẹ wò? [Jẹ́ kó fèsì, lẹ́yìn náà ka Éfésù 4:17.] Ìwé ìròyìn yìí ṣàlàyé bí àwọn òbí ṣe lè ran àwọn ọmọ wọn lọ́wọ́ kí wọ́n lè mọ irú fíìmù tàbí eré sinimá tó bójú mu fún wọn.”