ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 11/07 ojú ìwé 1
  • À Ń Wàásù Ìhìn Rere Ìjọba Ọlọ́run Fáwọn Ẹlòmíì

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • À Ń Wàásù Ìhìn Rere Ìjọba Ọlọ́run Fáwọn Ẹlòmíì
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jẹ́ Kí Ìrètí Tó O Ní Dá Ẹ Lójú
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
  • Ní Ìrètí Nínú Jèhófà Kó o Sì Jẹ́ Onígboyà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
  • Ibo Lo Ti Lè Rí Ìrètí Tòótọ́?
    Jí!—2004
  • Ìrètí Tó O Ní Ò Ní Já Ẹ Kulẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
km 11/07 ojú ìwé 1

À Ń Wàásù Ìhìn Rere Ìjọba Ọlọ́run Fáwọn Ẹlòmíì

1 Púpọ̀ nínú àwọn èèyàn tó ń gbé láwọn ọjọ́ ìkẹyìn tó le koko yìí ni ò gbà gbọ́ pé nǹkan ń bọ̀ wá dáa. (Éfé. 2:12) Àwọn míì ti fàìmọ̀kan gbẹ́kẹ̀ lé ọrọ̀, àwọn alákòóso ayé, ìmọ̀ sáyẹ́ǹsì, àtàwọn nǹkan míì. Ẹ ò ri bí ayọ̀ wa ti pọ̀ tó torí a mọ̀ pé nǹkan ṣì ń bọ̀ wá dáa! Mímọ̀ tá a mọ̀ pé nǹkan ń bọ̀ wá dáa yìí ni “ìdákọ̀ró fún ọkàn wa, ó dájú, ó [sì] fìdí múlẹ̀ gbọn-in.”—Héb. 6:19.

2 Nígbà tí Ìjọba Ọlọ́run bá ń ṣàkóso, ilẹ̀ ayé yóò di Párádísè. Àwọn olólùfẹ́ wa tí wọ́n ti kú máa jíǹde. (Ìṣe 24:15) Àìríná-àìrílò, ìwà ìrẹ́nijẹ, àìsàn, ọjọ́ ogbó àti ikú máa wábi gbà. (Sm. 9:18; Mát. 12:20, 21; Ìṣí. 21:3, 4) Díẹ̀ rèé lára àwọn ohun tí Jèhófà ti ṣèlérí pé òun yóò ṣe. Ó dáa ná, èwo lo máa fẹ́ kí Ọlọ́run kọ́kọ́ ṣe nínú àwọn ohun tó ṣèlérí wọ̀nyí?

3 Wàásù Ìhìn Rere: A ò gbọ́dọ̀ fi ìgbàgbọ́ tá a ní pé nǹkan ṣì ń bọ̀ wá dáa lábẹ́ Ìjọba Ọlọ́run mọ sọ́dọ̀ ara wa. Torí pé a nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run àtàwọn aládùúgbò wa, à ń fara wé Jésù bá a ṣe ń “polongo ìhìn rere fún àwọn òtòṣì,” tá à ń “wàásù ìtúsílẹ̀ fún àwọn òǹdè àti ìtúnríran fún àwọn afọ́jú,” tá a sì ń “rán àwọn tí a ni lára lọ pẹ̀lú ìtúsílẹ̀.” (Lúùkù 4:18) Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù wàásù ìhìn rere yìí nínú ọjà àti níbikíbi tó bá ti ráwọn èèyàn. Ó jẹ́ kí ọwọ́ òun dí jọjọ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù. (Ìṣe 18:5) Tá a bá fara wé Pọ́ọ̀lù tá a sì ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù, “àníyàn ètò àwọn nǹkan yìí àti agbára ìtannijẹ ọrọ̀” ò ní jẹ́ kí ìgbàgbọ́ tá a ní pé nǹkan ń bọ̀ wá dáa lábẹ́ Ìjọba Ọlọ́run wọ̀ọ̀kùn.—Máàkù 4:19.

4 A ò gbọ́dọ̀ jẹ́ kí ìgbàgbọ́ tá a ní nínú Ìjọba Ọlọ́run ṣákìí nígbà tá a bá pàdé àwọn tí ò fìfẹ́ hàn, àwọn tí ìfẹ́ tí wọ́n ní fún ọ̀rọ̀ nípa Ìjọba náà ò jinlẹ̀ tó tàbí àwọn tó ń ta kò wá lójú méjèèjì. Ńṣe ni ká yáa “di ìpolongo ìrètí wa ní gbangba mú ṣinṣin láìmikàn.” (Héb. 10:23) Ká sì má ṣe “tijú ìhìn rere.” (Róòmù 1:16) Ó wá lè jẹ́ pé rírí táwọn míì bá rí i pé ìgbàgbọ́ wa dá wa lójú tí wọ́n sì rí i pé à ń fara da àdánwò ló máa mú kí wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí tẹ́tí sí wa.

5 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé a máa ń sọ fáwọn èèyàn pé àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì tó ń nímùúṣẹ ló fà á tí ipò nǹkan fi ń burú si nínú ayé, síbẹ̀ a kì í ṣe oníwàásù ègbé. Kàkà bẹ́ẹ̀, ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run là ń wàásù. Ǹjẹ́ ká máa fìtara wàásù ìhìn rere yìí pẹ̀lú ìgbàgbọ́ tó dájú ká lè ní “ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìdánilójú ìrètí náà títí dé òpin.”—Héb. 6:11.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́