ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 12/07 ojú ìwé 1
  • Ẹ Má Ṣe Jẹ́ Kí Iná Ìtara Yín fún Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Jó Rẹ̀yìn

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ẹ Má Ṣe Jẹ́ Kí Iná Ìtara Yín fún Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Jó Rẹ̀yìn
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jẹ́ Kí “Iná Ẹ̀mí Máa Jó Nínú” Rẹ
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2009
  • Ṣé Wàá Jẹ́ Onítara Bíi Ti Jèhófà àti Jésù Nígbà Ìrántí Ikú Kristi Tó Ń Bọ̀ Yìí?
    Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2015
  • Máa Fi Ìtara Wàásù Nìṣó
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Ṣé Ò Ń Tọ Kristi Lẹ́yìn Nígbà Gbogbo?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2007
km 12/07 ojú ìwé 1

Ẹ Má Ṣe Jẹ́ Kí Iná Ìtara Yín fún Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Jó Rẹ̀yìn

1 Láti ọdún 1992, ó ju bílíọ̀nù kan wákàtí lọ táwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà fi ń fìtara wàásù ìhìn rere Ìjọba Ọlọ́run kárí ayé lọ́dọọdún, tá a sì ń sọ àwọn èèyàn dọmọ ẹ̀yìn. Ẹ ò rí i bí ayọ̀ wa ti pọ̀ tó láti ṣe ìwọ̀nba ohun tá a lè ṣe nínú àṣeyọrí tó kàmàmà yìí!—Mát. 28:19, 20.

2 Kò sí àníàní pé Jèhófà ló yẹ ká fọpẹ́ fún, torí pé òun ló ń mú ká ṣàṣeyọrí nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa láwọn “àkókò lílekoko” yìí. (2 Tím. 3:1) Kí ló yẹ ká ṣe tá a bá fẹ́ máa bá a lọ ní fífi ìtara ṣe iṣẹ́ pàtàkì yìí?

3 Ohun Tó Ń Jẹ́ Ká Nítara: Ìfẹ́ àtọkànwá tá a ní sí Ọlọ́run àtàwọn aládùúgbò wa àti ìpinnu wa láti mú ẹ̀jẹ́ ìyàsímímọ́ wa ṣẹ ló ń mú ká máa fìtara ṣe iṣẹ́ ìsìn Ìjọba Ọlọ́run. (Mát. 22:37-39; 1 Jòh. 5:3) Ìfẹ́ tá a ní ló ń jẹ́ ká lè yááfì àwọn nǹkan kan ká bàa lè ṣe púpọ̀ sí i nínú iṣẹ́ ìwàásù.—Lúùkù 9:23.

4 Ẹ Sapá Kí Ìtara Yín Má Bàa Jó Rẹ̀yìn: Gbogbo ọ̀nà ni elénìní wa, Èṣù, ń gbà láti rí i pé òun pa iná ìtara tá a ní fún iṣẹ́ ìwàásù. Ìrònú nípa àwọn tí ò fìfẹ́ hàn ní ìpínlẹ̀ ìwàásù wa, ipò nǹkan tí ò fara rọ, ọ̀ràn àtijẹ àtimu àti ara wa tó túbọ̀ ń di hẹ́gẹhẹ̀gẹ lójoojúmọ́ wulẹ̀ jẹ́ díẹ̀ lára àwọn ohun tí Èṣù ń lò láti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wa.

5 Nítorí náà, a gbọ́dọ̀ sapá gidigidi kí iná ìtara wa lè máa jó fòfò. Ó ṣe pàtàkì pé ká jẹ́ kí “ìfẹ́ [tá a] ní ní àkọ́kọ́” máa wà lọ́kàn wa. Ìyẹn ni pé ká máa ka Bíbélì, Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run déédéé, ká sì máa ṣàṣàrò lórí rẹ̀. Ká máa lo gbogbo ohun tí Jèhófà ń tipasẹ̀ “ẹrú olóòótọ́ àti olóye” pèsè kí ìgbàgbọ́ wa nínú Rẹ̀ má bàa ṣákìí.—Ìṣí. 2:4; Mát. 24:45; Sm. 119:97.

6 Báwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ṣe jẹ́ ká mọ̀, Jèhófà máa tó pa àwọn ẹni búburú run. (2 Pét. 2:3; 3:10) Níwọ̀n bá a ti mọ̀ bẹ́ẹ̀, ẹ jẹ́ ká sapá gidigidi kí iná ìtara wa lè máa jó ròkè lálá bá a ti ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe nínú iṣẹ́ wíwàásù Ìjọba Ọlọ́run àti sísọni dọmọ ẹ̀yìn, tó ń lọ lọ́wọ́ báyìí kárí ayé!

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́