ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/10 ojú ìwé 2
  • Ǹjẹ́ Mò Ń Ṣe Tó Bó Ṣe Yẹ?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ǹjẹ́ Mò Ń Ṣe Tó Bó Ṣe Yẹ?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ǹjẹ́ o Nífẹ̀ẹ́ Àwọn Ìránnilétí Jèhófà Lọ́nà Tó Kọyọyọ?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2000
  • Àwọn Ìránnilétí Jèhófà Ṣeé Gbẹ́kẹ̀ Lé
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Jẹ́ Kí Àwọn Ìránnilétí Jèhófà Máa Múnú Rẹ Dùn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ǹjẹ́ Ò Ń Ṣe Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Rẹ Láṣeyanjú?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2010
km 7/10 ojú ìwé 2

Ǹjẹ́ Mò Ń Ṣe Tó Bó Ṣe Yẹ?

1. Àwọn nǹkan wo ló lè mú kí Kristẹni kan tó jẹ́ olóòótọ́ máa ṣàníyàn?

1 Ṣé o ti bi ara rẹ ní ìbéèrè yìí rí? Ó lè jẹ́ pé ara tó ti ń di ara àgbà, àìlera tàbí ojúṣe rẹ tó ń pọ̀ sí i nínú ìdílé ni kò jẹ́ kó o lè kópa nínú iṣẹ́ òjíṣẹ́ bíi ti ìgbà kan, èyí sì ń mú kó o rẹ̀wẹ̀sì. Arábìnrin kan tó ní ọmọ mẹ́ta kọ̀wé pé, nígbà míì ọkàn òun máa ń dá òun lẹ́bi torí àkókò àti okun tóun fi ń bójú tó ìdílé òun kò jẹ́ kóun lè ṣe tó bóun ṣe fẹ́ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́. Kí ló máa ràn wá lọ́wọ́ láti ní èrò tó tọ́ nípa ìwọ̀n tá a lè ṣe lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́?

2. Kí ni Jèhófà ń retí pé ká ṣe?

2 Ohun Tí Jèhófà Retí Lọ́wọ́ Wa: Kò sí àní-àní pé gbogbo wa la máa fẹ́ ṣe púpọ̀ sí i lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́. Àmọ́ lọ́pọ̀ ìgbà, ìyàtọ̀ gbọ̀ọ̀rọ̀ gbọọrọ ló máa ń wà láàárín ohun tá a máa ń fẹ́ ṣe àti ohun tí agbára wa gbé. Bó ṣe ń wù wá láti ṣe púpọ̀ sí i fi hàn pé a kò dẹra nù. Ó yẹ ká máa rántí nígbà gbogbo pé Jèhófà mọ ibi tí agbára wa mọ, kò sì béèrè ohun tó ju agbára wa lọ. (Sm. 103:13, 14) Kí ni Jèhófà ń retí pé ká ṣe? Ó fẹ́ ká sin òun tọkàntọkàn, ká sì ṣe gbogbo ohun tí agbára wa bá gbé.—Kól. 3:23.

3. Báwo la ṣe lè díwọ̀n ibi tí agbára wa mọ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́?

3 Kí ló máa jẹ́ ká lè mọ ohun tí agbára wa gbé? A lè bẹ Jèhófà pé kó jẹ́ ká mọ ibi tí agbára wa mọ lóòótọ́. (Sm. 26:2) A lè wá ìrànlọ́wọ́ Kristẹni tá a fọkàn tán, tí òtítọ́ jinlẹ̀ nínú rẹ̀, tó sì jẹ́ ọ̀rẹ́ tí kò ní fọ̀rọ̀ sábẹ́ ahọ́n sọ nígbà tó bá ń sọ àwọn àtúnṣe tó yẹ ká ṣe. (Òwe 27:9) Tún rántí pé, á dáa ká máa ṣàyẹ̀wò ara wa látìgbàdégbà torí pé àwọn nǹkan máa ń yí pa dà.—Éfé. 5:10.

4. Ojú wo ló yẹ ká máa fi wo àwọn ìránnilétí látinú Bíbélì nípa iṣẹ́ òjíṣẹ́ wa?

4 Ojú Tó Yẹ Ká Máa Fi Wo Àwọn Ìránnilétí: Nígbà táwọn sárésáré bá ń sáré, àwọn òǹwòran á máa pariwo orúkọ àwọn tó ń sáré. Ìdí tí wọ́n sì fi ń ṣe bẹ́ẹ̀ ni láti fún wọn níṣìírí kí wọ́n lè ṣàṣeyọrí, kì í ṣe láti kó ìrẹ̀wẹ̀sì bá wọn. Bákan náà, àǹfààní wa ni àwọn ìṣírí àti ìránnilétí tá a gbé ka Bíbélì, tá à ń rí gbà láwọn ìpàdé ìjọ àti nínú àwọn ìtẹ̀jáde wa, pé ká máa ‘wàásù ọ̀rọ̀ náà ní kánjúkánjú’ wà fún, kò túmọ̀ sí pé a kò ṣe tó bó ṣe yẹ lẹ́nu iṣẹ́ òjíṣẹ́. (2 Tím. 4:2) Ẹ jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà máa rántí ‘ìfẹ́ àti iṣẹ́’ wa, yóò sì bù kún wa, tá a bá ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe.—Héb. 6:10.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́