ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 1/14 ojú ìwé 1
  • Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì—Míkà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì—Míkà
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • A Óò Máa Rìn Ní Orúkọ Jèhófà Títí Láé!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Àwọn Ìránṣẹ́ Jèhófà Ní Ìrètí Tòótọ́
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Kí Ni Jèhófà Ń Retí Pé Ká Máa Ṣe?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Báwo La Ṣe Lè Máa Ní “Ẹ̀mí Ìdúródeni”?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
km 1/14 ojú ìwé 1

Tẹ̀ Lé Àpẹẹrẹ Àwọn Wòlíì​—Míkà

1. Ìbéèrè wo ló ṣeé ṣe kí Míkà ti ronú lé lórí, kí sì nìdí tá a fi lè sọ pé ìwàásù rẹ̀ kò já sí asán?

1 ‘Ìgbà wo ni ètò àwọn nǹkan búburú yìí máa wá sópin?’ Ó ṣeé ṣe kí wòlíì Míkà ti ronú lórí irú ìbéèrè yìí nígbà tó ń kéde ìdájọ́ Jèhófà lórí ìjọba Ísírẹ́lì àti Júdà. Síbẹ̀, ìwàásù rẹ̀ kò já sí asán. Àsọtẹ́lẹ̀ Jèhófà nípa Samáríà ṣẹ nígbà ayé Míkà, ìyẹn lọ́dún 740 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni. (Míkà 1:6, 7) Nígbà tó yá, Jerúsálẹ́mù pa run lọ́dún 607 Ṣáájú Sànmánì Kristẹni. (Míkà 3:12) Lákòókò tiwa yìí, báwo la ṣe lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Míkà bí a ṣe ń dúró de ìgbà tí Jèhófà máa mú ìdájọ́ rẹ̀ wá?

2. Báwo la ṣe ń fi hàn pé a mú sùúrù bí a ti ń dúró de ọjọ́ Jèhófà, kí sì nìdí tó fi yẹ ká ṣe bẹ́ẹ̀?

2 Ẹ Mú Sùúrù: Míkà sọ pé: “Ní tèmi, Jèhófà ni èmi yóò máa wá. Dájúdájú, èmi yóò fi ẹ̀mí ìdúródeni hàn sí Ọlọ́run ìgbàlà mi.” (Míkà 7:7) Míkà ò kàn jókòó tẹtẹrẹ bó ṣe ń dúró de ìgbà tí òpin máa dé. Ó ń bá iṣẹ́ wòlíì rẹ̀ lọ. Bí a ṣe ń dúró de ọjọ́ Jèhófà, ó yẹ káwa náà máa kópa nínú “ìṣe ìwà mímọ́ àti àwọn iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run.” (2 Pét. 3:11, 12) Bí Jèhófà ṣe ní sùúrù ń fáwọn èèyàn láǹfààní láti ronú pìwà dà. (2 Pét. 3:9) Nítorí náà, a fi ìtọ́ni Ọlọ́run sọ́kàn pé káwa náà mú sùúrù bíi ti àwọn wòlíì.—Ják. 5:10.

3. Kí nìdí tó fi yẹ ká bẹ Jèhófà pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀?

3 Gbára Lé Jèhófà Kó Lè Fún Ẹ Lókun: Iṣẹ́ tí Ọlọ́run gbé fún Míkà kò rọrùn, àmọ́ ohun tó fún un lókun tó fi lè ṣàṣeyọrí ni pé ó gbára lé Jèhófà. (Míkà 3:8) Abájọ tí Ọ̀rọ̀ Jèhófà fi rọ̀ wá pé ká gbára lé Ọlọ́run kó lè fún wa lókun. Ìwà ọ̀làwọ́ Ọlọ́run máa ń mú kó fún àwọn tó ti rẹ̀ lágbára kí wọ́n lè ṣe ojúṣe wọn lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn rẹ̀. (Sm. 84:5, 7; Aísá. 40:28-31) Ṣé ìwọ náà ti rí okùn gbà látọ̀dọ̀ Ọlọ́run látìgbà tó o ti ń sìn ín? Ṣé o máa ń bẹ́ Jèhófà déédéé pé kó fi ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ ràn ẹ́ lọ́wọ́ kó lè fún ẹ lókun?—Lúùkù 11:13.

4. Báwo ni ìgbé ayé Míkà ṣe jẹ́ àpẹẹrẹ àtàtà fún wa lónìí?

4 Iṣẹ́ ìsìn Ọlọ́run ló ṣe pàtàkì jù sí Míkà nígbà ayé rẹ̀. Ó pinnu pé òun máa jẹ́ olóòótọ́ sí Ọlọ́run bó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn oníwàkiwà ló yí i ká. Bíi ti Míkà, ojoojúmọ́ làwa náà ń rí ohun tó ń dán ìwà títọ́ wa wò. Nítorí náà, ẹ jẹ́ kí a dúró lórí ìpinnu wa pé a ó “máa rìn ní orúkọ Jèhófà Ọlọ́run wa fún àkókò tí ó lọ kánrin, àní títí láé.”—Míkà 4:5.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́