ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • km 7/14 ojú ìwé 2
  • Báwo Ni Mo Ṣe Rí Lójú Jèhófà?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Báwo Ni Mo Ṣe Rí Lójú Jèhófà?
  • Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Máa Fi Bíbélì Yẹ Ara Ẹ Wò Bíi Dígí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2025
  • Má Ṣe Jẹ́ Kí ‘Ìfẹ́ Tó O Ní Lákọ̀ọ́kọ́’ Jó Rẹ̀yìn
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2008
  • Ọ̀nà Méje Téèyàn Lè Gbà Jàǹfààní Látinú Bíbélì Kíkà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • Máa Fi Hàn Pé O Ní Ẹ̀mí Ìfara-Ẹni-Rúbọ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
Àwọn Míì
Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Ìjọba Wa—2014
km 7/14 ojú ìwé 2

Báwo Ni Mo Ṣe Rí Lójú Jèhófà?

1. Báwo ni Bíbélì ṣe dà bí dígí?

1 Ìgbà mélòó lo máa ń wo ara rẹ nínú dígí lóòjọ́? Ojúmọ́ kan kì í lọ kí èyí tó pọ̀ jù nínú wa má wo dígí torí ó máa ń jẹ́ ká rí àwọn ibi tó ń fẹ́ àtúnṣe lára wa. A lè fi Bíbélì wé dígí. Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run máa ń jẹ́ ká mọ irú ẹni tá a jẹ́ gan-an, ìyẹn sì ni Jèhófà ń wò. (1 Sám. 16:7; Ják. 1:22-24.) Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run “lè fi òye mọ ìrònú àti àwọn ìpètepèrò ọkàn-àyà.” (Héb. 4:12) Báwo ni kíka Bíbélì lójoojúmọ́ àti ṣíṣàṣàrò lórí ohun tá a kà ṣe lè jẹ́ ká rí àwọn ibi tó yẹ ká ti sunwọ̀n sí i ká lè túbọ̀ kẹ́sẹ járí lẹ́nu iṣẹ́ ajíhìnrere?—Sm. 1:1-3.

2. Báwo la ṣe lè fi Bíbélì ṣàyẹ̀wò ara wa?

2 Máa Lo Bíbélì Bí I Dígí: Ìtàn àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà tó wà nínú Bíbélì kọ́ wa láwọn ànímọ́ tó wu Jèhófà. Bí àpẹẹrẹ, Dáfídì ní ìtara fún orúkọ Ọlọ́run. (1 Sám. 17:45, 46) Aísáyà fìgboyà yọ̀ǹda ara rẹ̀ láti lọ wàásù ní ìpínlẹ̀ tí iṣẹ́ ìwàásù ti ṣòro gan-an. (Aísá. 6:8, 9) Ìfẹ́ tó jinlẹ̀ tí Jésù ní sí Baba rẹ̀ ọ̀run mú kó ka iṣẹ́ òjíṣẹ́ rẹ̀ sí orísun ìtura àti ìtẹ́lọ́rùn dípò kó kà á sí ẹrù ìnira. (Jòh. 4:34) Àwọn Kristẹni ọgọ́rùn-ún ọdún kìíní fi ìtara wàásù, wọ́n gbára lé Jèhófà, wọ́n sì pinnu pé àwọn kò ní juwọ́ sílẹ̀. (Ìṣe 5:41, 42; 2 Kọ́r. 4:1; 2 Tím. 4:17) Tá a bá ń ronú jinlẹ̀ lórí àwọn àpẹẹrẹ bí èyí, yóò jẹ́ ká lè ṣàyẹ̀wò ara wa lọ́nà tí a ó fi lè mú kì iṣẹ́ ìsìn mímọ́ wa sunwọ̀n sí i.

3. Kí nìdí tí kò fi yẹ ká máa fi àtúnṣe tó yẹ ká ṣe falẹ̀?

3 Gbé Ìgbésẹ̀ Láti Ṣàtúnṣe Tó Bá Yẹ: Kò sí àǹfààní kankan nínú ká wo ara wa nínú dígí ká sì má ṣe àtúnṣe tó yẹ síbi tó kù díẹ̀ káàtó. A lè bẹ Jèhófà pé kó ràn wá lọ́wọ́ ká lè ṣàyẹ̀wò ara wa lọ́nà tó tọ́, kó sì ràn wá lọ́wọ́ láti ṣàtúnṣe tó bá yẹ. (Sm. 139:23, 24; Lúùkù 11:13) Torí pé àkókò tó ṣẹ́ kù kò tó nǹkan mọ́, ẹ̀mí àwọn èèyàn sì wà nínú ewu, kò yẹ ká máa fi àtúnṣe tó yẹ ká ṣe falẹ̀ rárá.—1 Kọ́r. 7:29; 1 Tím. 4:16.

4. Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sí ẹni tó bá ń wo inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó sì ń ṣiṣẹ́ lórí ohun tó rí?

4 Ohun tí Jèhófà ń wò, ìyẹn ẹni tí a jẹ́ gan-an ṣe pàtàkì ju bí ìrísí wa ṣe rí lọ. (1 Pét. 3:3, 4) Kí ló máa ṣẹlẹ̀ sí ẹni tó bá ń wo inú Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tó sì ń ṣiṣẹ́ lórí ohun tó rí? “Ẹni yìí, nítorí tí kò di olùgbọ́ tí ń gbàgbé, bí kò ṣe olùṣe iṣẹ́ náà, yóò láyọ̀ nínú ṣíṣe é.” (Ják. 1:25) Láìsí tàbí-ṣùgbọ́n, a máa ní ayọ̀, a ó sì di òjíṣẹ́ tó jáfáfá torí à ń ṣe “àgbéyọ ògo Jèhófà bí i dígí.”—2 Kọ́r. 3:18.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́