ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb17 August ojú ìwé 8
  • Àwọn Ànímọ́ Kristẹni Tó Yẹ Kó O Ní​—Ìgbàgbọ́

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àwọn Ànímọ́ Kristẹni Tó Yẹ Kó O Ní​—Ìgbàgbọ́
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Fún Wa Ní Ìgbàgbọ́ Sí I”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2015
  • Ìgbàgbọ́—Ànímọ́ Tó Ń Sọni Di Alágbára
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2019
  • Máa Lo Ìgbàgbọ́ Nínú Àwọn Ìlérí Jèhófà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2016
  • Ṣé Lóòótọ́ Lo Nígbàgbọ́ Nínú Ìhìn Rere?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Àwa Kristẹni​—Ìwé Ìpàdé (2017)
mwb17 August ojú ìwé 8

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Àwọn Ànímọ́ Kristẹni Tó Yẹ Kó O Ní​—Ìgbàgbọ́

ÌDÍ TÓ FI ṢE PÀTÀKÌ:

  • A gbọ́dọ̀ ní ìgbàgbọ́ ká lè ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run dáadáa.​—Heb 11:6

  • Tá a bá gba àwọn ìlérí Ọlọ́run gbọ́, èyí á jẹ́ ká lè fara da àdánwò.​—1Pe 1:​6, 7

  • Tá ò bá ní ìgbàgbọ́, èyí lè mú ká dẹ́ṣẹ̀. ​—Heb 3:​12, 13

BÓ O ṢE LÈ ṢE É:

  • Gbàdúrà sí Ọlọ́run pé kó fún ẹ ní ìgbàgbọ́ sí i.​—Lk 11:​9, 13; Ga 5:22

  • Máa ka Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, kí o sì máa ṣàṣàrò lórí rẹ̀.​—Ro 10:17; 1Ti 4:15

  • Máa ṣọ̀rẹ́ pẹ̀lú àwọn ẹni ìgbàgbọ́. ​—Ro 1:​11, 12

Tọkọtaya kan ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa àwọn àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì tó máa ṣẹ láìpẹ́

Báwo ni mo ṣe lè mú kí ìgbàgbọ́ tèmi àti ti ìdílé mi túbọ̀ lágbára?

WO FÍDÍÒ NÁÀ MÁA LÉPA OHUN TÓ LÈ MÚ KÓ O JẸ́ ADÚRÓṢINṢIN​—ÌGBÀGBỌ́, LẸ́YÌN NÁÀ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Kí ni “ìgbàgbọ́ láìsí àgàbàgebè”? (1Ti 1:5)

  • Tá a bá fẹ́ ní ìgbàgbọ́ tó lágbára, àwọn nǹkan tí kò dára wo la gbọ́dọ̀ yẹra fún?

  • Kí nìdí tó fi máa pọn dandan pé ká ní ìgbàgbọ́ nígbà ìpọ́njú ńlá? (Heb 10:39)

ṢÀṢÀRÒ LÓRÍ ÀPẸẸRẸ INÚ BÍBÉLÌ:

Ábúráhámù lo ìgbàgbọ́ nínú Jèhófà, kódà nígbà tí kò rọrùn fún un láti ṣe bẹ́ẹ̀. ​—Heb 11:​8-10, 17-19.

Bi ara rẹ pé, ‘Báwo ni mo ṣe lè ní ìgbàgbọ́ bíi ti Ábúráhámù?’

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́