ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb18 February ojú ìwé 3
  • Àkàwé Àlìkámà àti Èpò

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Àkàwé Àlìkámà àti Èpò
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • “Àwọn Olódodo Yóò Máa Tàn Yòò Bí Oòrùn”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2010
  • “Wò Ó! Mo Wà Pẹ̀lú Yín Ní Gbogbo Àwọn Ọjọ́”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2013
  • Ìsìn Kristẹni Tòótọ́ Kan Ṣoṣo—Ló Wà
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Ta Ni Ọ̀tá Ìgbàgbọ́ Òdodo?
    Ìgbàgbọ́ Òdodo Ló Máa Mú Kó O Ní Ayọ̀
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2018
mwb18 February ojú ìwé 3

ÀWỌN ÌṢÚRA INÚ Ọ̀RỌ̀ ỌLỌ́RUN | MÁTÍÙ 12-13

Àkàwé Àlìkámà àti Èpò

Jésù lo àlìkámà àti èpò láti ṣàpèjúwe bí òun ṣe máa yan àwọn ẹni àmì òróró tó dúró fún àlìkámà láti ara aráyé, bẹ̀rẹ̀ ní ọdún 33 Sànmàní Kristẹni.

Àtẹ ìsọfúnni nípa bá a ṣe gbin irúgbìn, bá a ṣe kórè, àti bá a ṣe kó irè náà sínú ilé ìtọ́jú-nǹkan-pa-mọ́

13:24

‘Ọkùnrin kan fún irúgbìn àtàtà sínú pápá rẹ̀’

  • Afúnrúgbìn: Jésù Kristi

  • Ó fún irúgbìn àtàtà: Ó fi ẹ̀mí mímọ́ yan àwọn ọmọ ẹ̀yìn

  • Pápá: Ayé

13:25

“Nígbà tí àwọn ènìyàn ń sùn, ọ̀tá wá fún èpò sínú pápá”

  • Ọ̀tá: Èṣù

  • Àwọn èèyàn ń sùn: Ikú àwọn àpọ́sítélì

13:30

“Ẹ jẹ́ kí àwọn méjèèjì dàgbà pa pọ̀ títí di ìkórè”

  • Àlìkámà: Àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró

  • Èpò: Àwọn Kristẹni afàwọ̀rajà

“Ẹ kọ́kọ́ kó àwọn èpò jọ . . . ; lẹ́yìn náà ẹ lọ kó àlìkámà jọ”

  • Àwọn ẹrú tàbí akárúgbìn: Àwọn áńgẹ́lì

  • Èpò tí wọ́n kó jọ: Wọ́n ya àwọn Kristẹni afàwọ̀rajà kúrò lára àwọn ẹni àmì òróró

  • Kíkójọ sínú ilé ìtọ́jú-nǹkan-pa-mọ́: Wọ́n kó àwọn Kristẹni ẹni àmì òróró jọ sínú ìjọ tá a mú pa dà bọ̀ sípò

Nígbà tí ìkórè bẹ̀rẹ̀, kí ló mú kí àwọn Kristẹni tòótọ́ yàtọ̀ sí àwọn Kristẹni afàwọ̀rajà?

Àǹfààní wo ni mo rí nínú ìtumọ̀ àkàwé yìí?

ǸJẸ́ O MỌ̀?

Àlìkámà àti èpò ń dàgbà pọ̀

Ó ṣeé ṣe kí èpò tí Jésù ń sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀ nínú àpèjúwe rẹ̀ jẹ́ àwọn èpò kan báyìí tó máa ń ní irun lára. Kí irúgbìn onímájèlé yìí tó dàgbà, ó máa ń fara jọ àlìkámà gan-an. Bí àlìkámà àti èpò náà ṣe ń dàgbà pọ̀, ìdí wọn á bẹ̀rẹ̀ sí í so kọ́ra, èyí máa ń mú kó ṣòro láti yọ èpò kúrò láìba àlìkámà náà jẹ́. Àmọ́ tí èèyàn bá jẹ́ kí èpò náà dàgbà, á rọrùn fún akárúngbìn láti dá èyí tí òun fẹ́ yọ kúrò mọ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́