ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb21 May ojú ìwé 7
  • Ìfẹ́ Ló Ń Mú Kí Jèhófà Bá Wa Wí

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìfẹ́ Ló Ń Mú Kí Jèhófà Bá Wa Wí
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Mímọrírì Ìdí Tá A Fi Ń Báni Wí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Báwo Ni Ìbáwí Ṣe Ń Fi Hàn Pé Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Wa?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
  • Bí O Ṣe Lè Bá Àwọn Ọmọ Rẹ Wí
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2014
  • ‘Fetí sí Ìbáwí Kó O sì Di Ọlọ́gbọ́n’
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2018
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
mwb21 May ojú ìwé 7
Ọmọkùnrin kan tó ti tójú bọ́ dẹ́ṣẹ̀, kò sì ronú pìwà dà, torí náà àwọn òbí ẹ̀ ń sunkún lẹ́nu ọ̀nà nígbà tó ń filé sílẹ̀.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Ìfẹ́ Ló Ń Mú Kí Jèhófà Bá Wa Wí

Wọ́n máa ń bá wa wí ká lè mọ ohun tó yẹ ká ṣe, àmọ́ nígbà míì ó lè gba pé kí wọ́n tọ́ wa sọ́nà tàbí kí wọ́n fìyà jẹ wá torí àṣìṣe tá a ṣe. Jèhófà máa ń bá wa wí ká lè máa jọ́sìn rẹ̀ lọ́nà tó fẹ́. (Ro 12:1; Heb 12:​10, 11) Ìbáwí máa ń dùn wá nígbà míì, àmọ́ tá a bá gbà á, á jẹ́ ká ṣe ohun tí Jèhófà fẹ́, Jèhófà á sì bù kún wa. (Owe 10:7) Kí ló yẹ kí ẹni tó ń báni wí àtẹni tí wọ́n ń bá wí fi sọ́kàn?

Ẹni tó ń báni wí. Ó yẹ káwọn alàgbà, àwọn òbí àtàwọn míì gbìyànjú láti finúure hàn tí wọ́n bá ń báni wí, kí wọ́n sì fìfẹ́ ṣe é bíi ti Jèhófà. (Jer 46:28) Kódà, tó bá gba pé kí wọ́n bá ẹnì kan wí lọ́nà tó múná, kí wọ́n ṣe é ní ìwọ̀ntún-wọ̀nsì àti lọ́nà tá fi hàn pé wọ́n nífẹ̀ẹ́ ẹni náà.​—Tit 1:13.

Ẹni tí wọ́n ń bá wí. Dípò tí àá fi máa ronú nípa bẹ́nì kan ṣe bá wa wí, ṣe ló yẹ ká gba ìbáwí náà, ká sì fi sílò lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. (Owe 3:​11, 12) Aláìpé ni gbogbo wa, torí náà a nílò ìbáwí, oríṣiríṣi ọ̀nà ni wọ́n sì lè gbà bá wa wí. Ó lè jẹ́ ohun tá a kà látinú Bíbélì tàbí ohun tá a gbọ́ nípàdé. Nígbà míì sì rèé, ó lè gba pé kí ìgbìmọ̀ onídàájọ́ bá wa wí. Àmọ́ tá a bá gba ìbáwí tá a sì fi sílò, ó máa ṣe wá láǹfààní, ìyẹn á sì jẹ́ ká wà láàyè títí láé.​—Owe 10:17.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ “ÀWỌN TÍ JÈHÓFÀ NÍFẸ̀Ẹ́ LÓ MÁA Ń BÁ WÍ,” KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Àwọn Tí Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Ló Máa Ń Bá Wí.’ Nígbà tí Canon wà ní kékeré, òun àtàwọn òbí ẹ̀ ń wàásù.

    Báwo ni nǹkan ṣe rí fún Canon nígbà tó wà ní kékeré, àmọ́ kí ló ṣẹlẹ̀ nígbà tó yá?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Àwọn Tí Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Ló Máa Ń Bá Wí.’ Nígbà tí Canon wà lọ́dọ̀ọ́, ó ń bá àwọn alàgbà sọ̀rọ̀.

    Báwo ni Jèhófà ṣe fìfẹ́ bá a wí?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Àwọn Tí Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Ló Máa Ń Bá Wí.’ Canon ti di àgbàlagbà báyìí, ó ń bá àwọn ọ̀dọ́ sọ̀rọ̀ nínú Gbọ̀ngàn Ìjọba.

    Jẹ́ kó mọ́ ẹ lára láti máa gba ìbáwí Jèhófà

    Kí la rí kọ́ látinú ohun tó ṣẹlẹ̀ sí i?

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́