ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb21 May ojú ìwé 13
  • Máa Fìfẹ́ Hàn Nínú Ìdílé

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Máa Fìfẹ́ Hàn Nínú Ìdílé
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìdílé Rẹ Lè Láyọ̀
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Ohun Tó O Lè Ṣe Kí Ìdílé Rẹ Lè Jẹ́ Aláyọ̀
    Kí Ni Bíbélì Fi Kọ́ni Gan-an?
  • Ìgbésí Ayé Ìdílé Tí Inú Ọlọrun Dùn Sí
    Kí Ni Ọlọ́run Ń Béèrè Lọ́wọ́ Wa?
  • Kọ́kọ́rọ́ Méjì sí Ìgbéyàwó Wíwà Pẹ́ Títí
    Àṣírí Ayọ̀ Ìdílé
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2021
mwb21 May ojú ìwé 13
Ìdílé kan jọ ń kọrin pa pọ̀ nípàdé.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Máa Fìfẹ́ Hàn Nínú Ìdílé

Ìfẹ́ ló máa ń so àwọn tó wà nínú ìdílé pọ̀. Tí ò bá sí ìfẹ́, ìdílé ò ní wà níṣọ̀kan, wọn ò sì ní fọwọ́sowọ́pọ̀. Báwo làwọn ọkọ, aya àtàwọn òbí ṣe lè máa fìfẹ́ hàn nínú ìdílé?

Tí ọkọ kan bá nífẹ̀ẹ́ ìyàwó ẹ̀, á máa ka ohun tó nílò sí pàtàkì, á máa tẹ́tí sí i, á sì máa gba tiẹ̀ rò. (Ef 5:28, 29) A máa pèsè ohun tí ìdílé rẹ̀ nílò nípa tara àti nípa tẹ̀mí, á sì máa rí i pé òun ń ṣe Ìjọsìn Ìdílé déédéé. (1Ti 5:8) Tí aya kan bá nífẹ̀ẹ́ ọkọ ẹ̀, á máa tẹrí ba fún un, á sì ní “ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀” fún un. (Ef 5:22, 33; 1Pe 3:1-6) Àwọn méjèèjì gbọ́dọ̀ máa dárí ji ara wọn ní fàlàlà. (Ef 4:32) Òbí tó bá nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ ẹ̀ máa jẹ́ kó dá ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn lójú pé lóòótọ́ lòun nífẹ̀ẹ́ wọn, á sì máa kọ́ wọn láti nífẹ̀ẹ́ Jèhófà. (Di 6:6, 7; Ef 6:4) Á gbìyànjú láti mọ ohun táwọn ọmọ náà ń kojú nílé ìwé àtohun tí wọ́n ń ṣe táwọn ọ̀rẹ́ wọn bá fẹ́ mú kí wọ́n ṣe ohun tí ò dáa. Tí ìfẹ́ bá wà nínú ìdílé, gbogbo àwọn tó wà nínú ìdílé náà lọ́kàn wọn máa balẹ̀.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ MÁA FI ÌFẸ́ TI KÌ Í YẸ̀ HÀN NÍNÚ ÌDÍLÉ, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Ti Kì Í Yẹ̀ Hàn Nínú Ìdílé.’ Tọkọtaya kan jọ ń jíròrò ẹsẹ Bíbélì kan lẹ́yìn tí wọ́n dé láti ìpàdé.

    Báwo ni ọkọ tó nífẹ̀ẹ́ ìyàwó ẹ̀ á ṣe máa bọ́ ọ, tá sì máa ṣìkẹ́ ẹ̀?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Ti Kì Í Yẹ̀ Hàn Nínú Ìdílé.’ Lẹ́yìn tí arábìnrin kan dé láti ìpàdé, ó ń fara balẹ̀ tẹ́tí sí ọkọ ẹ̀ tí kì í ṣe Ẹlẹ́rìí Jèhófà, ó sì jẹ́ kó dá a lójú pé òun nífẹ̀ẹ́ rẹ̀.

    Báwo ni ìyàwó tó nífẹ̀ẹ́ ọkọ ẹ̀ ṣe lè fi ọ̀wọ̀ tó jinlẹ̀ hàn sí i?

  • Àwòrán látinú fídíò ‘Máa Fi Ìfẹ́ Ti Kì Í Yẹ̀ Hàn Nínú Ìdílé.’ Ìdílé kan ń jẹ ìpápánu, wọ́n sì ń sọ àwọn nǹkan tí wọ́n gbádùn nípàdé.

    Báwo làwọn òbí tó nífẹ̀ẹ́ àwọn ọmọ wọn ṣe lè máa kọ́ wọn ní Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run?

OHUN TÓ YẸ KÁWỌN ÒBÍ FI SỌ́KÀN NÍPA Ẹ̀RỌ ÌGBÀLÓDÉ

Téèyàn bá ń lo ọ̀pọ̀ àkókò nídìí ẹ̀rọ ìgbàlódé, ìyẹn lè mú kó nira fáwọn tó wà nínú ìdílé láti máa lo àkókò pa pọ̀, kí ìfẹ́ àárín wọn lè lágbára sí i. Torí náà, àwọn òbí lè ṣètò iye àkókò tí àwọn àtàwọn ọmọ wọn á máa lò nídìí ẹ̀. Àwọn òbí tún gbọ́dọ̀ pinnu bóyá àwọn ọmọ wọn ti lè lo ìkànnì àjọlò, kí wọ́n sì mọ irú ẹni táwọn ọmọ wọn ń bá sọ̀rọ̀ lórí ẹ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́