ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • mwb22 March ojú ìwé 13
  • Bópẹ́bóyá, Kò Sí Ìṣòro Tí Ò Ní Dópin

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Bópẹ́bóyá, Kò Sí Ìṣòro Tí Ò Ní Dópin
  • Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Jèhófà Ń Ràn Wá Lọ́wọ́ Lákòókò Ìṣòro
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2023
  • Ẹ Máa Ní Sùúrù
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2023
  • Ṣé Wàá Lè Fi Sùúrù Dúró De Jèhófà?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2017
  • Fi Sùúrù Dúró De Jèhófà
    Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
Àwọn Míì
Ìgbésí Ayé àti Iṣẹ́ Òjíṣẹ́ Kristẹni—Ìwé Ìpàdé—2022
mwb22 March ojú ìwé 13
Àwòrán: Apá kan nínú fídíò “Àwọn Èèyàn Tó Wà Níṣọ̀kan Nínú Ayé Tó Pín Yẹ́lẹyẹ̀lẹ.” 1. Àwùjọ àwọn arákùnrin àtàwọn arábìnrin tó jẹ́ aláwọ̀ dúdú ní àpéjọ kan. 2. Àwọn arákùnrin aláwọ̀ dúdú àti aláwọ̀ funfun tó jẹ́ alàgbà ń ya fọ́tò pẹ̀lú ìyàwó wọn. 3. Àwọn arábìnrin méjì tí ọjọ́ orí àti àwọ̀ wọn yàtọ̀ síra ń wàásù níbi térò pọ̀ sí.

MÁA HÙWÀ TÓ YẸ KRISTẸNI

Bópẹ́bóyá, Kò Sí Ìṣòro Tí Ò Ní Dópin

Ìṣòro máa ń kó ìrẹ̀wẹ̀sì báni, pàápàá tó bá jẹ́ ìṣòro tí ò lọ bọ̀rọ̀. Dáfídì mọ̀ pé ọjọ́ kan ń bọ̀ tóun máa bọ́ lọ́wọ́ Ọba Sọ́ọ̀lù, òun sì máa di ọba bí Jèhófà ṣe ṣèlèrí fún òun. (1Sa 16:13) Ìgbàgbọ́ tí Dáfídì ní yìí ló mú kó ní sùúrù, kó sì dúró de Jèhófà.

Tá a bá níṣòro, a sábà máa ń ronú nípa ọgbọ́n tá a lè dá tàbí ohun tá a lè ṣe láti yanjú ìṣòro náà. (1Sa 21:12-14; Owe 1:4) Bó ti wù kó rí, àwọn ìṣòro kan kì í lọ láìka bá a ṣe sapá tó láti fi ìlànà Bíbélì yanjú wọn. Nírú àwọn ipò bẹ́ẹ̀, a gbọ́dọ̀ ní sùúrù dìgbà tí Jèhófà máa dá sí ọ̀rọ̀ náà. Láìpẹ́, Jèhófà máa fòpin sí ìyà tó ń jẹ wá, á sì “nu gbogbo omijé” kúrò ní ojú wa. (Ifi 21:4) Yálà Jèhófà ló yanjú ìṣòro wa tàbí nǹkan míì ló ṣẹlẹ̀ tó mú kí ìṣòro náà lọ, ohun kan dájú: Bópẹ́bóyá, kò sí ìṣòro tí ò ní dópin. Ìrètí yìí lè fi wá lọ́kàn balẹ̀ tá a bá níṣòro.

Ẹ WO FÍDÍÒ NÁÀ ÀWỌN ÈÈYÀN TÓ WÀ NÍṢỌ̀KAN NÍNÚ AYÉ TÓ PÍN YẸ́LẸYẸ̀LẸ, KẸ́ Ẹ SÌ DÁHÙN ÀWỌN ÌBÉÈRÈ YÌÍ:

  • Ìṣòro wo làwọn ará wa ní gúúsù orílẹ̀-èdè Amẹ́ríkà dojú kọ?

  • Kí ni wọ́n ṣe tó fi hàn pé wọ́n ní sùúrù, wọ́n sì nífẹ̀ẹ́ ara wọn?

  • Kí ni wọ́n ṣe tó fi hàn pé “àwọn ohun tó ṣe pàtàkì jù” ni wọ́n gbájú mọ́?​—Flp 1:10

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́