ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • w20 June ojú ìwé 14-16
  • Ìkóra-Ẹni-Níjàánu—Ànímọ́ Táá Jẹ́ Ká Rí Ojúure Jèhófà

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìkóra-Ẹni-Níjàánu—Ànímọ́ Táá Jẹ́ Ká Rí Ojúure Jèhófà
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • KÍ NI ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU?
  • KÍ NÌDÍ TÍ ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU FI ṢE PÀTÀKÌ?
  • BÍ A ṢE LÈ NÍ ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU
  • TÁ A BÁ WÁ ṢÀÌ KÓ ARA WA NÍJÀÁNU ŃKỌ́?
  • Mímú Eso Ikora-ẹni-Nijaanu Dàgbà
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Ikora-ẹni-nijaanu—Eeṣe Ti Ó Fi Ṣe Pataki Tobẹẹ?
    Ilé-Ìṣọ́nà Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1991
  • Kó Ara Rẹ Níjàánu Kí o Lè Gba Èrè Náà!
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
  • Ẹ Fi Ìkóra-ẹni-níjàánu Kún Ìmọ̀ Yín
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2003
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2020
w20 June ojú ìwé 14-16

Ìkóra-Ẹni-Níjàánu​—Ànímọ́ Táá Jẹ́ Ká Rí Ojúure Jèhófà

  • ÌFẸ́

  • AYỌ̀

  • ÀLÀÁFÍÀ

  • SÙÚRÙ

  • INÚ RERE

  • ÌWÀ RERE

  • ÌGBÀGBỌ́

  • ÌWÀ TÚTÙ

  • ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU

“Nígbà tí èmi àti mọ̀lẹ́bí mi kan ní èdèkòyédè, mo gbá a mú, mo sì fún un lọ́rùn. Ṣe ló dá bíi pé kí n pa á.”​—Paul.

“Mi ò kì í pẹ́ bínú, mo sì máa ń gbaná jẹ mọ́ àwọn tá a jọ ń gbélé. Kò sóhun tí mi ò lè bà jẹ́, ó lè jẹ́ àga tàbí ohun ìṣeré ọmọdé.”​—Marco.

Ọ̀rọ̀ tiwa lè má le tó ti Paul àti Marco. Síbẹ̀ gbogbo wa la nílò ìkóra-ẹni-níjàánu. Ohun tó sì fà á ni pé a ti jogún ẹ̀ṣẹ̀ látọ̀dọ̀ Ádámù. (Róòmù 5:12) Àwọn kan máa ń bínú sódì bíi tàwọn méjì tá a sọ̀rọ̀ wọn yìí. Èrò òdì ló sì máa ń gba àwọn míì lọ́kàn. Wọ́n lè máa ronú ṣáá nípa ohun tó ń kó ẹ̀dùn ọkàn bá wọn. Ní tàwọn míì, ṣe ni wọ́n ń tiraka kí wọ́n má bàa lọ́wọ́ nínú ìṣekúṣe, ọtí àmujù tàbí ìlòkulò oògùn.

Àbámọ̀ ló sábà máa ń gbẹ̀yìn ẹ̀ fáwọn tí kì í kápá èrò wọn, ohun tọ́kàn wọn ń fà sí àti ìwà wọn. Àmọ́ a ò ní kábàámọ̀ nígbèésí ayé wa tá a bá kóra wa níjàánu. Ká lè kó ara wa níjàánu, ẹ jẹ́ ká jíròrò àwọn ìbéèrè mẹ́ta yìí: (1) Kí ni ìkóra-ẹni-níjàánu? (2) Kí nìdí tó fi ṣe pàtàkì? (3) Báwo lèèyàn ṣe lè ní ànímọ́ tó jẹ́ apá kan “èso ti ẹ̀mí” yìí? (Gál. 5:​22, 23) Lẹ́yìn náà, a máa jíròrò ohun tẹ́nì kọ̀ọ̀kan wa lè ṣe tó bá ṣòro fún wa láti kó ara wa níjàánu.

KÍ NI ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU?

Ẹni tó ń kó ara ẹ̀ níjàánu kì í ṣe nǹkan láìronú jinlẹ̀. Ó máa ń kíyè sára kó má bàa sọ̀rọ̀ tàbí ṣe ohun tó máa múnú bí Jèhófà.

Aṣáájú ìsìn Júù kan gbá Jésù létí lójú àwọn Sànhẹ́dírìn, àwọn náà sì fọwọ́ sí i. Kódà àwọn kan di ẹ̀ṣẹ́, wọ́n sì ń pariwo mọ́ Jésù.

Ó dájú pé Jésù kó ara ẹ̀ níjàánu gan-an

Jésù fi àpẹẹrẹ tó dáa lélẹ̀ lórí kókó yìí. Bíbélì sọ pé: “Nígbà tí wọ́n sọ̀rọ̀ àbùkù sí i, kò sọ̀rọ̀ àbùkù sí wọn pa dà. Nígbà tó ń jìyà, kò bẹ̀rẹ̀ sí í halẹ̀, àmọ́ ó fi ara rẹ̀ sí ìkáwọ́ Ẹni tó ń dájọ́ òdodo.” (1 Pét. 2:23) Ohun tí Jésù ṣe gẹ́lẹ́ nìyẹn nígbà tó wà lórí òpó igi oró táwọn alátakò sì ń fi ṣe yẹ̀yẹ́. (Mát. 27:​39-44) Ṣáájú ìgbà yẹn, Jésù ò sọ̀rọ̀ láìronú nígbà táwọn alátakò fẹ́ dẹkùn mú un. (Mát. 22:​15-22) Ẹ ò rí i pé àpẹẹrẹ àtàtà ló fi lélẹ̀ nígbà táwọn Júù fẹ́ sọ ọ́ lókùúta! Dípò tó fi máa sọ̀rọ̀ burúkú sí wọn, ṣe ni “Jésù fara pa mọ́, ó sì kúrò nínú tẹ́ńpìlì.”​—Jòh. 8:​57-59.

Ṣé a máa lè ṣe bíi ti Jésù? A lè ṣe bẹ́ẹ̀ déwọ̀n àyè kan. Àpọ́sítélì Pétérù sọ pé: “Kristi . . . jìyà torí yín, ó fi àpẹẹrẹ lélẹ̀ fún yín kí ẹ lè máa tọ ipasẹ̀ rẹ̀ pẹ́kípẹ́kí.” (1 Pét. 2:21) Bá a tiẹ̀ jẹ́ aláìpé, a lè tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù pẹ́kípẹ́kí ká sì ní ìkóra-ẹni-níjàánu. Kí nìdí tíyẹn fi ṣe pàtàkì?

KÍ NÌDÍ TÍ ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU FI ṢE PÀTÀKÌ?

Ó ṣe pàtàkì ká máa kó ara wa níjàánu tá a bá fẹ́ rí ojúure Jèhófà. A lè ti pẹ́ nínú òtítọ́, síbẹ̀ tá ò bá kó ara wa níjàánu lọ́rọ̀ àti níṣe, àjọṣe wa pẹ̀lú Jèhófà lè bà jẹ́.

Ẹ wo àpẹẹrẹ Mósè tí Bíbélì sọ pé ó “jẹ́ oníwà pẹ̀lẹ́ jù lọ nínú gbogbo èèyàn tó wà láyé” nígbà yẹn. (Nọ́ń. 12:3) Lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ọdún tó ti fara da ìwà àwọn ọmọ Ísírẹ́lì, ó ṣìwà hù lọ́jọ́ kan. Ó bínú sí wọn nígbà tí wọ́n ráhùn pé àwọn ò rómi mu. Ló bá fìkanra sọ fún wọn pé: “Ẹ gbọ́, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀! Ṣé látinú àpáta yìí ni ká ti fún yín lómi ni?”​—Nọ́ń. 20:​2-11.

Ó hàn pé Mósè ò kóra ẹ̀ níjàánu. Kò gbé ògo fún Jèhófà tó mú káwọn èèyàn náà rómi mu lọ́nà ìyanu. (Sm. 106:​32, 33) Fún ìdí yìí, Jèhófà ò jẹ́ kó wọ Ilẹ̀ Ìlérí. (Nọ́ń. 20:12) Ó ṣeé ṣe kí Mósè kábàámọ̀ ohun tó ṣe yìí títí tó fi kú.​—Diu. 3:​23-27.

Kí la rí kọ́? Bó ti wù ká pẹ́ tó nínú ètò Jèhófà, a gbọ́dọ̀ kíyè sára ká má bàa sọ̀rọ̀ burúkú sáwọn tó múnú bí wa tàbí sí àwọn tá a fẹ́ tọ́ sọ́nà. (Éfé. 4:32; Kól. 3:12) Ká sòótọ́, béèyàn ṣe ń dàgbà sí i ló máa ń nira féèyàn láti rí ara gba nǹkan. Àmọ́ ká máa rántí Mósè. Ká má ṣe jẹ́ kí àjọṣe tá a ní pẹ̀lú Jèhófà bà jẹ́ torí àìní ìkóra-ẹni-níjàánu. Báwo la ṣe lè ní ànímọ́ pàtàkì yìí?

BÍ A ṢE LÈ NÍ ÌKÓRA-ẸNI-NÍJÀÁNU

Bẹ Jèhófà pé kó fún ẹ ní ẹ̀mí mímọ́. Kí nìdí? Ìdí ni pé apá kan èso ti ẹ̀mí ni ìkóra-ẹni-níjàánu, tá a bá sì béèrè fún ẹ̀mí mímọ́ Jèhófà, ó máa fún wa. (Lúùkù 11:13) Jèhófà máa ń lo ẹ̀mí mímọ́ rẹ̀ láti fún wa lókun. (Fílí. 4:13) Ó tún lè ràn wá lọ́wọ́ láti ní àwọn apá míì lára èso ti ẹ̀mí bí ìfẹ́ tó máa jẹ́ ká túbọ̀ kó ara wa níjàánu.​—1 Kọ́r. 13:5.

Ọ̀dọ́kùnrin kan tó dá wà nínú yàrá ẹ̀ gbójú kúrò nígbà tí àwòrán tí kò bojú mu yọjú nínú kọ̀ǹpútà rẹ̀.

Sá fún ohunkóhun tó lè mú kó nira fún ẹ láti kó ara ẹ níjàánu

Sá fún ohunkóhun tó lè mú kó nira fún ẹ láti kó ara ẹ níjàánu. Ṣe ni kó o sá fún àwọn ìkànnì àtàwọn eré tó ń gbé ìṣekúṣe àti ìwà àìmọ́ lárugẹ. (Éfé. 5:​3, 4) Àní sẹ́, má tiẹ̀ sún mọ́ ohunkóhun tó lè mú kó o ro èròkerò tàbí hùwàkiwà. (Òwe 22:3; 1 Kọ́r. 6:12) Bí àpẹẹrẹ, ó máa bọ́gbọ́n mu kí ẹni tọ́kàn ẹ̀ máa ń fà sí ìṣekúṣe yẹra pátápátá fún ìwé àtàwọn fíìmù tó ń gbé ìṣekúṣe lárugẹ.

Ó lè má fi bẹ́ẹ̀ rọrùn fún wa láti fi ìmọ̀ràn yìí sílò. Àmọ́ tá a bá sapá, Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ ká lè kó ara wa níjàánu. (2 Pét. 1:​5-8) Nípa bẹ́ẹ̀, àá lè máa ṣọ́ èrò wa, ọ̀rọ̀ wa àti ìwà wa. Àpẹẹrẹ Paul àti Marco tá a sọ níbẹ̀rẹ̀ sì jẹ́ ká rí i pé òótọ́ lọ̀rọ̀ yìí. Àpẹẹrẹ míì ni ti arákùnrin kan tó máa ń bínú tó sì máa ń gbaná jẹ mọ́ àwọn awakọ̀ míì tó bá ń wakọ̀ lójú pópó. Kí ló ṣe kó lè kápá ìbínú rẹ̀? Ó sọ pé: “Mo máa ń gbàdúrà gan-an lójoojúmọ́ pé kí Jèhófà ràn mí lọ́wọ́. Mo ka àwọn ìtẹ̀jáde wa tó sọ̀rọ̀ nípa ìkóra-ẹni-níjàánu, mo sì há àwọn ẹsẹ Ìwé Mímọ́ kan sórí. Òótọ́ ni pé ọjọ́ pẹ́ tí mo ti ń sapá, síbẹ̀ àràárọ̀ ni mo máa ń rán ara mi létí pé ó yẹ kí n kó ara mi níjàánu. Bákan náà, mo máa ń tètè kúrò nílé kó má bàa di pé mò ń kánjú tíyẹn á sì mú kí n máa kanra mọ́ àwọn míì lójú ọ̀nà.”

TÁ A BÁ WÁ ṢÀÌ KÓ ARA WA NÍJÀÁNU ŃKỌ́?

Lẹ́ẹ̀kọ̀ọ̀kan, a lè ṣàì kó ara wa níjàánu. Tírú ẹ̀ bá ṣẹlẹ̀, ojú lè tì wá láti gbàdúrà sí Jèhófà. Àmọ́, àsìkò yẹn gan-an ló yẹ ká gbàdúrà. Torí náà, ẹsẹ̀kẹsẹ̀ ni kó o gbàdúrà. Bẹ Jèhófà pé kó dárí jì ẹ́, pé kó ràn ẹ́ lọ́wọ́, kíwọ náà sì pinnu pé o ò ní ṣerú ẹ̀ mọ́. (Sm. 51:​9-11) Jẹ́ kó dá ẹ lójú pé Jèhófà máa ṣàánú rẹ, kò sì ní kó àdúrà àtọkànwá rẹ dà nù. (Sm. 102:17) Àpọ́sítélì Jòhánù rán wa létí pé ẹ̀jẹ̀ Jésù “ń wẹ̀ wá mọ́ kúrò nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀.” (1 Jòh. 1:7; 2:1; Sm. 86:5) Ṣó o rántí pé Jèhófà sọ fún wa pé ká máa dárí ji àwọn tó ṣẹ̀ wá? Torí náà, jẹ́ kó dá ẹ lójú pé ó máa dárí jì ẹ́.​—Mát. 18:​21, 22; Kól. 3:13.

Jèhófà bínú sí Mósè torí pé ó ṣìwà hù lọ́jọ́ kan nínú aginjù. Àmọ́ Jèhófà dárí jì í. Kódà Bíbélì pè é ní olóòótọ́, ó sì rọ̀ wá pé ká fara wé ìgbàgbọ́ rẹ̀. (Diu. 34:10; Héb. 11:​24-28) Òótọ́ ni pé Jèhófà ò jẹ́ kí Mósè wọ Ilẹ̀ Ìlérí, àmọ́ ó máa jí i dìde nígbà tí ayé yìí bá di Párádísè, á sì fún un láǹfààní láti wà láàyè títí láé. Ó máa ṣeé ṣe fáwa náà láti wà láàyè títí láé tá a bá ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe ká lè ní ànímọ́ pàtàkì yìí, ìyẹn ìkóra-ẹni-níjàánu.​—1 Kọ́r. 9:25.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́