ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp24 No. 1 ojú ìwé 14-15
  • Ohun Tó Dáa àti Ohun Tí Kò Dáa: Pinnu Ohun Tí Wàá Ṣe

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ohun Tó Dáa àti Ohun Tí Kò Dáa: Pinnu Ohun Tí Wàá Ṣe
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2024
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ṣé A Ṣì Lè Gbára Lé Àwọn Ìlànà Bíbélì Lórí Ohun Tó Tọ́ àti Ohun Tí Kò Tọ́?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Máa Sin Jèhófà Ní Ìbámu Pẹ̀lú Àwọn Ìlànà Tó Fi Lélẹ̀
    Máa Fi Ọjọ́ Jèhófà Sọ́kàn
  • Àwa Èèyàn Jèhófà Nífẹ̀ẹ́ Òdodo
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2022
  • Ìlànà Ta Ni O Lè Gbẹ́kẹ̀ Lé?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2001
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2024
wp24 No. 1 ojú ìwé 14-15
Ọ̀dọ́kùnrin tá a rí àwòrán ẹ̀ nínú àwọn àpilẹ̀kọ tó ṣáájú ti dé téńté orí òkè tó ń lọ, ó wá gbójú sókè, inú ẹ̀ sì ń dùn.

Ohun Tó Dáa àti Ohun Tí Kò Dáa: Pinnu Ohun Tí Wàá Ṣe

Ìlànà tá a bá yàn láti tẹ̀ lé ló máa pinnu bóyá a máa láyọ̀ àbí a ò ní láyọ̀. Jèhófà náà mọ̀ bẹ́ẹ̀, ìdí nìyẹn tó fi ń rọ̀ wá pé ká máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà òun.

Jèhófà fẹ́ ká láyọ̀ kí ọkàn wa sì balẹ̀.

“Èmi, Jèhófà, ni Ọlọ́run rẹ, Ẹni tó ń kọ́ ọ kí o lè ṣe ara rẹ láǹfààní, Ẹni tó ń jẹ́ kí o mọ ọ̀nà tó yẹ kí o máa rìn. Ká ní o fetí sí àwọn àṣẹ mi ni! Àlàáfíà rẹ ì bá dà bí odò, òdodo rẹ ì bá sì dà bí ìgbì òkun.”—Àìsáyà 48:17, 18.

Torí pé Ọlọ́run ló dá wa, ó mọ ohun tó máa jẹ́ káyé wa dáa. Ó ní ká máa tẹ̀ lé ìmọ̀ràn òun, torí wọ́n máa ṣe wá láǹfààní. Tá a bá ń pa òfin Ọlọ́run mọ́, a ò ní máa bẹ̀rù bóyá ohun tá a ṣe dáa àbí kò dáa. Gbogbo ìgbà làá máa ṣe ohun tó dáa, torí náà inú wa á máa dùn, ọkàn wa á sì balẹ̀.

Jèhófà ò retí pé ká ṣe ohun tó kọjá agbára wa.

“Àṣẹ tí mò ń pa fún ọ lónìí yìí kò nira jù fún ọ, kì í sì í ṣe ohun tí kò sí lárọ̀ọ́wọ́tó rẹ.”—Diutarónómì 30:11.

Tá a bá fẹ́ máa tẹ̀ lé ìlànà Jèhófà, ó lè gba pé ká yí ìwà àti ìrònú wa pa dà. Àmọ́, Jèhófà ò retí pé ká ṣe ohun tó ju agbára wa lọ. Ó ṣe tán, òun ni Ẹlẹ́dàá wa, ó sì mọ ohun tí agbára wa gbé. Bá a bá ṣe ń mọ Jèhófà sí i, bẹ́ẹ̀ làá máa rí i pé “àwọn àṣẹ rẹ̀ kò nira.”—1 Jòhánù 5:3.

Àwọn obìnrin méjì tí wọ́n jẹ́ Ẹlẹ́rìí Jèhófà ń fi ìwé “Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!” kọ́ obìnrin kan lẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì.

Jèhófà ṣèlérí pé òun máa ran àwọn tó bá ń tẹ̀ lé ìlànà òun lọ́wọ́.

“Èmi Jèhófà Ọlọ́run rẹ ń di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mú, Ẹni tó ń sọ fún ọ pé, ‘Má bẹ̀rù. Màá ràn ọ́ lọ́wọ́.’”—Àìsáyà 41:13.

A lè ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́, torí ó dájú pé ó máa ràn wá lọ́wọ́. Ó lè lo Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀ láti ràn wá lọ́wọ́, kó lè fún wa níṣìírí, ká sì lè ní ìrètí.

Ọ̀pọ̀ èèyàn kárí ayé ló ti rí i pé nígbà tí wọ́n ń ṣe ohun tí Bíbélì sọ, ńṣe layé wọn ń dáa sí i. Ìwọ náà máa rí ọ̀pọ̀ àǹfààní tó o bá kẹ́kọ̀ọ́ sí i, kó o lè mọ àwọn ìmọ̀ràn àtàtà tó wà nínú Bíbélì. O lè bẹ̀rẹ̀ ìkẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì látinú ìwé Gbádùn Ayé Rẹ Títí Láé!—Ìbẹ̀rẹ̀ Ẹ̀kọ́ Bíbélì. Ìwé yìí wà lórí jw.org, ọ̀fẹ́ lo sì máa wà á jáde. Àwọn ẹ̀kọ́ tó wà nínú ìwé náà rèé:

  • Ṣé Bíbélì Lè Ràn Ẹ́ Lọ́wọ́?

  • Bíbélì Sọ Pé Ọ̀la Ń Bọ̀ Wá Dáa

  • Kí Nìdí Tó Fi Yẹ Kó O Gbára Lé Bíbélì?

Tó o bá fara balẹ̀ kẹ́kọ̀ọ́ Bíbélì Ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, wàá rí i pé ọ̀rọ̀ inú ẹ̀ ṣì wúlò gan-an, ó sì “ṣeé gbára lé ní gbogbo ìgbà, ní báyìí àti títí láé.” (Sáàmù 111:8) Ohun tó dáa jù tá a lè ṣe ni pé ká máa tẹ̀ lé àwọn ìlànà Bíbélì, torí ìyẹn ló máa jẹ́ káyé wa dáa. Àmọ́, Ọlọ́run ò ní fipá mú wa pé ká tẹ̀ lé ìlànà òun. (Diutarónómì 30:19, 20; Jóṣúà 24:15) Ẹnì kọ̀ọ̀kan wa ló máa yàn bóyá òun máa ṣe bẹ́ẹ̀ àbí òun ò ní ṣe bẹ́ẹ̀.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́