ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp25 No. 1 ojú ìwé 9
  • Ìdí Táwọn Èèyàn Ò Fi Lè Dáwọ́ Ogun àti Rògbòdìyàn Dúró

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Ìdí Táwọn Èèyàn Ò Fi Lè Dáwọ́ Ogun àti Rògbòdìyàn Dúró
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ẹ̀ṢẸ̀
  • ÌJỌBA ÈÈYÀN
  • SÁTÁNÌ ÀTÀWỌN Ẹ̀MÍ ÈṢÙ
  • Bí Ogun àti Rògbòdìyàn Ṣe Máa Dópin
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
  • Kí Ni Ọlọ́run Ní Lọ́kàn fún Aráyé?
    Kí Ni Bíbélì Kọ́ Wa?
  • Ki Ni Ẹ̀ṣẹ̀ Ìpilẹ̀ṣẹ̀?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Gbogbo Wa Ni Ogun àti Rògbòdìyàn Ń Ṣàkóbá Fún
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
wp25 No. 1 ojú ìwé 9

Ìdí Táwọn Èèyàn Ò Fi Lè Dáwọ́ Ogun àti Rògbòdìyàn Dúró

Bíbélì jẹ́ ká mọ ìdí tí ogun àti rògbòdìyàn fi ń ṣẹlẹ̀ kárí ayé. Ó tún jẹ́ ká mọ ìdí táwọn èèyàn ò fi lè dáwọ́ ẹ̀ dúró.

Ẹ̀ṢẸ̀

Ọlọ́run dá àwọn òbí wa àkọ́kọ́, Ádámù àti Éfà ní àwòrán ara ẹ̀. (Jẹ́nẹ́sísì 1:27) Ìyẹn ni pé wọ́n á lè gbé àwọn ìwà àti ìṣe Ọlọ́run yọ, tó fi mọ́ àlàáfíà àti ìfẹ́. (1 Kọ́ríńtì 14:33; 1 Jòhánù 4:8) Àmọ́, Ádámù àti Éfà ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run wọ́n sì dẹ́ṣẹ̀. Bó ṣe di pé gbogbo èèyàn jogún ẹ̀ṣẹ̀ àti ikú látọ̀dọ̀ wọn nìyẹn. (Róòmù 5:12) Ẹ̀ṣẹ̀ tá a jogún yìí ló ń mú káwọn èèyàn máa ro èrò burúkú kí wọ́n sì máa dá wàhálà sílẹ̀.—Jẹ́nẹ́sísì 6:5; Máàkù 7:21, 22.

ÌJỌBA ÈÈYÀN

Ọlọ́run ò dá wa ká máa ṣàkóso ara wa. Bíbélì sọ pé: “Kò sí ní ìkáwọ́ èèyàn tó ń rìn láti darí ìṣísẹ̀ ara rẹ̀.” (Jeremáyà 10:23) Torí náà, ìjọba èèyàn ò lè fòpin sí ogun àti rògbòdìyàn pátápátá.

SÁTÁNÌ ÀTÀWỌN Ẹ̀MÍ ÈṢÙ

Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé “gbogbo ayé wà lábẹ́ agbára ẹni burúkú náà.” (1 Jòhánù 5:19) Sátánì Èṣù ni “ẹni burúkú náà,” apààyàn sì ni. (Jòhánù 8:44) A ò lè rí òun àtàwọn ẹ̀mí èṣù ẹ̀, àmọ́ àwọn ló wà nídìí ogun àti rògbòdìyàn tó ń ṣẹlẹ̀ láyé.—Ìfihàn 12:9, 12.

Ọlọ́run nìkan ló lè fòpin sí ohun tó ń fa ogun àti rògbòdìyàn láyé yìí, agbára àwa èèyàn ò ká a.

Àwọn Ẹlẹ́sìn Ń Ti Ogun Lẹ́yìn

Ẹ̀sìn sábà máa ń fọwọ́ sí ogun, wọn ò sì rí ohun tó burú nínú ẹ̀. Ẹ̀sìn èké làwọn ẹ̀sìn yìí, àwọn sì ni Bíbélì pè ní “Bábílónì Ńlá.” (Ìfihàn 18:2) Ọlọ́run dá Bábílónì Ńlá lẹ́bi torí ikú “gbogbo àwọn tí wọ́n pa ní ayé.” (Ìfihàn 18:24) Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i, ka àpilẹ̀kọ náà “Kí Ni Bábílónì Ńlá?” lórí jw.org.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́