ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • wp25 No. 1 ojú ìwé 4-5
  • Gbogbo Wa Ni Ogun àti Rògbòdìyàn Ń Ṣàkóbá Fún

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Gbogbo Wa Ni Ogun àti Rògbòdìyàn Ń Ṣàkóbá Fún
  • Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìgbà Wo Ni Gbogbo Ogun Yìí Máa Dópin?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Wọ́n Ti Ná Ẹgbẹ̀lẹ́gbẹ̀ Owó Sórí Ogun—Kí Ni Àbárèbábọ̀ Ẹ̀?
    Àkójọ Àpilẹ̀kọ àti Fídíò
  • Bí Ogun àti Rògbòdìyàn Ṣe Máa Dópin
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
  • Ogun
    Jí!—2017
Àwọn Míì
Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tá À Ń Fi Sóde)—2025
wp25 No. 1 ojú ìwé 4-5
Àwòrán: 1. Sójà kan ń rìn nínú pápá, ọkọ̀ tí wọ́n fi ń jagun sì ń bọ̀ lẹ́yìn ẹ̀. 2. Àwọn èèyàn lọ́kùnrin, lóbìnrin, lọ́mọdé àti lágbà tí ogun ti hàn léèmọ̀, tí wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀.

Gbogbo Wa Ni Ogun àti Rògbòdìyàn Ń Ṣàkóbá Fún

“Látìgbà Ogun Àgbáyé Kejì, ńṣe ni ogun àti rògbòdìyàn túbọ̀ ń pọ̀ sí i láyé. Kódà, ó tó bílíọ̀nù méjì èèyàn tó ń gbé láwọn agbègbè tí ìlú ò ti rọgbọ, ìyẹn sì jẹ́ ìdá kan nínú mẹ́rin iye èèyàn tó wà láyé.”

Amina J. Mohammed, Igbákejì Akọ̀wé Àjọ Ìṣọ̀kan Àgbáyé, January 26, 2023.

Ìgbàkigbà ni ogun tàbí rògbòdìyàn lè bẹ̀rẹ̀, kódà láwọn ibi táwọn èèyàn kì í ti í bára wọn fa wàhálà. Ní báyìí tí ayé ti lu jára, ohun tó ń ṣẹlẹ̀ láwọn ibi tí ogun ti ń jà máa ń ṣàkóbá fáwọn ìlú tó jìnnà pàápàá. Ràbọ̀ràbọ̀ ẹ̀ kì í sì í tètè tán nílẹ̀. Ẹ jẹ́ ká wo àwọn àpẹẹrẹ kan:

  • Àwòrán ọwọ́ méjì tó di abọ́ mú.

    Ó máa ń fa àìtó oúnjẹ. Àjọ Tó Ń Bójú Tó Ọ̀rọ̀ Oúnjẹ Lágbàáyé sọ pé “ogun ni olórí ohun tó ń fa àìtó oúnjẹ kárí ayé. Èyí to pọ̀ jù lára àwọn tébi ń pa lágbàáyé ló jẹ́ pé agbègbè tí ogun ti ń jà tàbí tí rògbòdìyàn ti ń ṣẹlẹ̀ ni wọ́n ń gbé.”

  • Àwòrán obìnrin kan tó fọwọ́ bojú, tínú ẹ̀ ò sì dùn.

    Ó máa ń ṣàkóbá fún ìlera ara àti ọpọlọ. Tí ogun bá ń jà, ó máa ń kó ìdààmú bá àwọn èèyàn, kì í sì í jẹ́ kọ́kàn wọn balẹ̀. Láwọn agbègbè tí rògbòdìyàn ti sábá máa ń ṣẹlẹ̀, ìlera ara àwọn èèyàn nìkan kọ́ ni wàhálà náà máa ń ṣàkóbá fún, ó tún máa ń ṣàkóbá fún ìlera ọpọlọ wọn. Bẹ́ẹ̀ sì rèé, ọ̀pọ̀ ìgbà ló jẹ́ pé àwọn tó wà lágbègbè yẹn kì í rí ìtọ́jú tó yẹ gbà.

  • Àwòrán ìdílé kan tí wọ́n gbé àwọn báàgì ńlá sórí, ẹrù wọn ló sì wà nínú ẹ̀.

    Àwọn èèyàn máa ń sá kúrò nílé. Kọmíṣọ́nnà Àgbà fún Àjọ Ìṣọ̀kan Àgbáyé Tó Ń Rí Sí Ọ̀rọ̀ Àwọn Tó Ń Wá Ibi Ìsádi sọ pé, ní September 2023, ó ti ju mílíọ̀nù mẹ́rìnléláàádọ́fà (114 million) èèyàn tí wọ́n ti sá kúrò nílé kárí ayé. Èyí tó sì pọ̀ jù lára àwọn èèyàn yìí ló jẹ́ pé torí ogun tàbí rògbòdìyàn ni wọ́n ṣe sá kúrò nílé.

  • Àwòrán ìdílé kan tí wọ́n dúró síwájú ilé kékeré tí wọ́n ń gbé.

    Ọrọ̀ ajé máa ń dẹnu kọlẹ̀. Ogun sábà máa ń jẹ́ kí ọrọ̀ ajé dẹnu kọlẹ̀, torí ńṣe ni gbogbo nǹkan máa ń gbówó lórí. Ìjọba á wá máa fi owó tó wà nílùú bójú tó ọ̀rọ̀ ogun dípò kí wọ́n máa fi bójú tó ọ̀rọ̀ ìlera àti ètò ẹ̀kọ́. Owó kékeré kọ́ ni wọ́n sì máa ń ná láti fi tún àwọn nǹkan tí ogun ti bà jẹ́ ṣe.

  • Àwòrán páìpù kan tí epo ń tú jáde látinú ẹ̀.

    Ó máa ń ba nǹkan jẹ́. Ìyà máa ń jẹ àwọn èèyàn gan-an lásìkò ogun. Torí àwọn kẹ́míkà àtàwọn nǹkan olóró tí wọ́n fi ń jagun á ti ba ilẹ̀ àtàwọn nǹkan àmúṣọrọ̀ míì jẹ́, omi á ti di ẹlẹ́gbin, wọ́n á sì ti tú àwọn nǹkan olóró sínú afẹ́fẹ́. Èyí máa ń ṣàkóbá fún ìlera àwọn èèyàn, ó sì lè fa àìsàn olọ́jọ́ pípẹ́. Kódà, àwọn àdó olóró tó wà nínú ilẹ̀ ṣì lè ṣọṣẹ́ lẹ́yìn àkókò gígùn tí ogun ti parí.

Ká sòótọ́, ogun máa ń ba nǹkan jẹ́ gan-an, ó sì máa ń sọ orílẹ̀-èdè di ẹdun arinlẹ̀.

Àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì Nípa Ogun

Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé ogun àti rògbòdìyàn wà lára ohun tó máa fi hàn pé a ti wà ní “ìparí ètò àwọn nǹkan.” (Mátíù 24:3) Jésù Kristi sọ tẹ́lẹ̀ pé:

  • “Ẹ máa gbọ́ nípa àwọn ogun, ẹ sì máa gbọ́ ìròyìn nípa àwọn ogun. . . . Torí orílẹ̀-èdè máa dìde sí orílẹ̀-èdè àti ìjọba sí ìjọba.”—Mátíù 24:6, 7.

  • “Tí ẹ bá gbọ́ nípa ogun àti rògbòdìyàn, ẹ má bẹ̀rù.”—Lúùkù 21:9.

    Ọ̀rọ̀ èdè Hébérù tá a tú sí “rògbòdìyàn” tún lè túmọ̀ sí ìdàrúdàpọ̀, ọ̀tẹ̀ sí ìjọba àti ìjà òṣèlú.

Tó o bá fẹ́ mọ̀ sí i, lọ sí jw.org kó o ka àpilẹ̀kọ náà “Àwọn Àmì Wo Ló Fi Hàn Pé A Ti Wà Ní ‘Àwọn Ọjọ́ Ìkẹyìn,’ Tàbí ‘Òpin Ayé’?”

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́