ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwyp àpilẹ̀kọ 75
  • Kí Ni Kí Ń Ṣe Tí Ọ̀rẹ́ Mi Bá Ṣe Nǹkan Tó Dùn Mí?

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Kí Ni Kí Ń Ṣe Tí Ọ̀rẹ́ Mi Bá Ṣe Nǹkan Tó Dùn Mí?
  • Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ohun tó yẹ kó o mọ̀
  • Ohun tó o lè ṣe
  • Kí Nìdí Táwọn Ọ̀rẹ́ Mi Fi Ń Ṣe Ohun Tó Ń Dùn Mí?
    Àwọn Ìbéèrè Tí Àwọn Ọ̀dọ́ Ń Béèrè—Àwọn Ìdáhùn Tí Ó Gbéṣẹ́, Apá Kejì
  • Kí Ló Dé Táwọn Ọ̀rẹ́ Mi Fi Máa Ń Ṣe Nǹkan Tó Dùn Mí?
    Jí!—2000
  • Kí Ni Ìdáríjì?
    Ohun Tí Bíbélì Sọ
  • Má Ṣe Mú Kí “Àwọn Ẹni Kékeré Yìí” Kọsẹ̀
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa (Ẹ̀dà Tó Wà fún Ìkẹ́kọ̀ọ́)—2021
Àwọn Míì
Àwọn Ọ̀dọ́ Béèrè Pé
ijwyp àpilẹ̀kọ 75
Ọmọbìnrin kan ń sọ̀rọ̀ sí ọmọbìnrin míì

ÀWỌN Ọ̀DỌ́ BÉÈRÈ PÉ

Kí Ni Kí Ń Ṣe Tí Ọ̀rẹ́ Mi Bá Ṣe Nǹkan Tó Dùn Mí?

  • Ohun tó yẹ kó o mọ̀

  • Ohun tó o lè ṣe

  • Ohun táwọn ojúgbà rẹ sọ

Ohun tó yẹ kó o mọ̀

  • Arẹ́májà kan ò sí. Torí pé aláìpé ni gbogbo wa, ọ̀rẹ́ rẹ tímọ́tímọ́ lè ṣe nǹkan tó dùn ẹ́ gan-an. Má gbàgbé pé aláìpé ni ìwọ náà. Tíwọ náà bá rọ̀ ó dáadáa, wàá rántí pé nígbà kan rí, ìwọ náà ti ṣe nǹkan tó múnú bí ẹlòmíì.​—Jákọ́bù 3:2.

  • Ohun tí ọ̀rẹ́ rẹ gbé sórí ìkànnì lè múnú bí ẹ. Bí àpẹẹrẹ, ọ̀dọ́kùnrin kan tó ń jẹ́ David sọ pé: “Tó o bá rí i pé àwọn ọ̀rẹ́ rẹ fi fọ́tò tí wọ́n yà níbi àpèjẹ kan sórí ìkànnì àjọlò, o lè bẹ̀rẹ̀ sí í bínú sí wọn pé wọn ò pè ẹ́ wá síbi àpèjẹ náà. Á wá máa ṣe ẹ́ bíi pé àwọn ọ̀rẹ́ rẹ ti ṣe àìdáa sí ẹ, inú sì lè máa bí ẹ.”

  • Ìwọ fúnra rẹ lè yanjú ọ̀rọ̀ náà.

Ohun tó o lè ṣe

Yẹ ara rẹ wò. Bíbélì sọ pé: “Má ṣe kánjú nínú ẹ̀mí rẹ láti fara ya, nítorí pé fífara ya sinmi ní oókan àyà àwọn arìndìn.”​—Oníwàásù 7:9.

“Ọ̀pọ̀ ìgbà ni wàá wá rí i pé nǹkan tí ò tó nǹkan lò ń bínú sí.”​—Alyssa.

Bi ara rẹ pé: Ṣé gbogbo nǹkan ni mo máa ń bínú sí? Ṣé mo lè máa gbójú fo àìdáa táwọn míì bá ṣe sí mi?​—Oníwàásù 7:21, 22.

Àǹfààní tó wà nínú kéèyàn máa dárí jini. Bíbélì sọ pé: ‘Ẹwà ni ó jẹ́ láti gbójú fo ìrélànàkọjá.’​—Òwe 19:11.

“Kódà tó bá jẹ́ pé lóòótọ́ lẹnì kan ṣẹ̀ ẹ́, ohun tó dáa jù ni pé kó o dárí ji ẹni náà látọkànwá, kò ní dá a tó o bá ń rán ẹni yẹn létí ohun tó ṣe fún ẹ, kó lè máa bẹ̀ ẹ́ ní gbogbo ìgbà pé kó o má bínú. Tó o bá ti dárí ji ẹnì kan, gbàgbé ọ̀rọ̀ náà.”​—Mallory.

Bi ara rẹ pé: Ṣé ọ̀rọ̀ yìí tó bí mo ṣe ń rò ó? Ṣé mo lè dárí ji ẹni tó ṣẹ̀ mí kí àlàáfíà lè jọba?​—Kólósè 3:​13.

Ṣe lò ń ṣí ilẹ̀kùn sílẹ̀, tí òtútù sì ń fẹ́ wọ inú ilé

Tó ò bá kí ń gbàgbé ọ̀rọ̀ àná, ṣe ló dà bí ìgbà tóò ń ṣí ilẹ̀kùn sílẹ̀, tí òtútù sì ń fẹ́ wọ inú ilé

Má ṣe ro tara ẹ nìkan. Bíbélì sọ pé: “Ẹ má ṣe máa mójú tó ire ara ẹni nínú kìkì àwọn ọ̀ràn ti ara yín nìkan, ṣùgbọ́n ire ara ẹni ti àwọn ẹlòmíràn pẹ̀lú.”​—Fílípì 2:4.

“Tó o bá nífẹ̀ẹ́ àwọn ọ̀rẹ́ ẹ, tó o sì bọ̀wọ̀ fún wọn, wàá rí ìdí tó fi yẹ kó o tètè máa yanjú èdèkòyédè tó bá yọjú kí àárín yín má bàa dàrú. Torí ó ti pẹ́ tẹ́ ẹ ti ń bá ọ̀rẹ́ yín bọ̀.”​—Nicole.

Bi ara rẹ pé: Àwọn nǹkan tó dára wo ni mo rí nínú ohun táwọn míì sọ?​​—Fílípì 2:3.

Òótọ́ ibẹ̀ ni pé: Ìsinsìnyí tó o ṣì jẹ́ ọ̀dọ́ ló yẹ kó o mọ nǹkan tó o lè ṣe tó bá ń ṣe ẹ́ bíi pé ẹnì kan ti ṣẹ̀ ẹ́. Tó o bá túbọ̀ dàgbà, àwọn nǹkan yẹn máa ràn ẹ́ lọ́wọ́ gan-an.

Ohun táwọn ojúgbà rẹ sọ

Kiana

“Kì í ṣe gbogbo ọ̀rọ̀ ló yẹ ká máa pe ẹnì kan jókòó yanjú. Tó bá jẹ́ nǹkan tí mo lè gbé kúrò lọ́kàn ni, màá gbàgbẹ́ ẹ̀. Ìyẹn máa jẹ́ kí àlàáfíà jọba, dípò tí màá fi máa gba gbogbo ọ̀rọ̀ sí ìbínú.”​—Kiana.

Treigh

“Nígbà tọ́rọ̀ bá ṣẹlẹ̀, mo máa ń bi ara mi pé, ‘Ṣó yẹ kí ń jẹ́ kí ọ̀rọ̀ yìí da àárín èmi àti ọ̀rẹ́ mi rú?’ Kì í wù mí kírú ẹ̀ ṣẹlẹ̀ lọ́pọ̀ ìgbà.”​​—Treigh.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́