ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
  • ijwbv àpilẹ̀kọ 41
  • Oníwàásù 3:11—“Ó Ti Ṣe Ohun Gbogbo Dáradára ní Àsìkò Tirẹ̀”

Kò sí fídíò kankan ní apá yìí.

Má bínú, fídíò yìí kò jáde.

  • Oníwàásù 3:11—“Ó Ti Ṣe Ohun Gbogbo Dáradára ní Àsìkò Tirẹ̀”
  • Àlàyé Àwọn Ẹsẹ Bíbélì
  • Ìsọ̀rí
  • Àpilẹ̀kọ Míì Tó Jọ ọ́
  • Ìtumọ̀ Oníwàásù 3:11
  • Àwọn Ẹsẹ Tó Ṣáájú Àtèyí Tó Tẹ̀ Lé Oníwàásù 3:11
  • “Gbogbo Ojúṣe Ènìyàn”
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Ìgbésí Ayé Rẹ—Kí Ni Ète Rẹ̀?
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1997
  • Gbádùn Ayé Rẹ
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—1998
  • Àwọn Kókó Pàtàkì Látinú Ìwé Oníwàásù
    Ilé Ìṣọ́ Tí Ń Kéde Ìjọba Jehofa—2006
Àwọn Míì
Àlàyé Àwọn Ẹsẹ Bíbélì
ijwbv àpilẹ̀kọ 41

ÀLÀYÉ ÀWỌN ẸSẸ BÍBÉLÌ

Oníwàásù 3:11—“Ó Ti Ṣe Ohun Gbogbo Dáradára ní Àsìkò Tirẹ̀”

“Ó ti ṣe ohun gbogbo rèǹtèrente ní ìgbà tirẹ̀. Kódà ó ti fi ayérayé sí wọn lọ́kàn; síbẹ̀ aráyé ò lè rídìí iṣẹ́ tí Ọlọ́run tòótọ́ ti ṣe láé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.”—Oníwàásù 3:11, Ìtumọ̀ Ayé Tuntun.

“Ó ti ṣe ohun gbogbo dáradára ní àsìkò tirẹ̀, ó sì ti fi èrò nípa ayérayé sí ọkàn ọmọ ènìyàn, síbẹ̀, wọn kò le ṣe àwárí ìdí ohun tí Ọlọ́run ti ṣe láti ìbẹ̀rẹ̀ títí dé òpin.”—Oníwàásù 3:11, Bíbélì Mímọ́ Ní Èdè Yorùbá Òde Òní.

Ìtumọ̀ Oníwàásù 3:11

“Ó ti ṣe ohun gbogbo rèǹtèrente ní ìgbà tirẹ̀.” Kì í ṣe ohun tó rẹwà lójú nìkan ni Ọ̀rọ̀ Hébérù tá a túmọ̀ sí “rèǹtèrente” ń sọ̀rọ̀ nípa ẹ̀. Ó tún lè túmọ̀ sí kí nǹkan wà “létòlétò,” “lọ́nà tó yẹ,” tàbí “lọ́nà tó bá a mu.” (Oníwàásù 3:11, àlàyé ìsàlẹ̀ ìwé) Àwọn ohun tí Ọlọ́run dá àtàwọn ohun tó ń ṣe kí ìfẹ́ rẹ̀ lè ṣẹ jẹ́ ara àwọn iṣẹ́ rẹ̀ tó wà létòletò.—Dáníẹ́lì 2:21; 2 Pétérù 3:8; Ìfihàn 4:11.

“Kódà ó ti fi ayérayé sí wọn lọ́kàn.” Ọlọ́run dá àwa èèyàn láti wà láàyè títí láé. (Sáàmù 37:29) Torí náà, ó máa ń wù wá láti wà láàyè títí lọ. Àmọ́, Ádámù àti Éfà tó jẹ́ tọkọtaya àkọ́kọ́ ṣàìgbọràn sí Ọlọ́run, wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ fa ikú wá sórí ara wọn àtàwọn àtọmọdọ́mọ wọn. (Jẹ́nẹ́sísì 3:17-19; Róòmù 5:12) Síbẹ̀, Ọlọ́run ṣèlérí láti “fún gbogbo ohun alààyè ní ohun tí wọ́n ń fẹ́,” títí kan bó ṣe ń wù wọ́n láti wà láàyè títí láé. (Sáàmù 145:16) Bíbélì sọ nípa ohun tí Jèhófà ṣe kí èèyàn lè láǹfààní láti wà láàyè títí láé.—Róòmù 6:23.

“Aráyé ò lè rídìí iṣẹ́ tí Ọlọ́run tòótọ́ ti ṣe láé láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.” Ọgbọ́n Ọlọ́run pọ̀ débi ti Bíbélì fi sọ pé ó “kọjá àwárí.” (Róòmù 11:33) Síbẹ̀, Ọlọ́run ṣe tán láti fi àwọn ohun tó fẹ́ ṣe han àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.—Émọ́sì 3:7.

Àwọn Ẹsẹ Tó Ṣáájú Àtèyí Tó Tẹ̀ Lé Oníwàásù 3:11

Ọba Sólómọ́nì ti ilẹ̀ Ísírẹ́lì àtijọ́ ló kọ ìwé Oníwàásù, ọkùnrin yìí lókìkí gan-an torí ọgbọ́n tí Ọlọ́run fún un. Àwọn ìmọ̀ràn tó dá lórí ohun tó ṣe pàtàkì àtohun tí ò ní láárí nígbèésí ayé ló wà nínú ìwé yìí. (Oníwàásù 1:2, 3; 2:1, 17; 7:1; 12:1, 13) Ní orí kẹ́ta, àwọn ohun tó sábà máa ń ṣẹlẹ̀ nígbèésí ayé ni Sólómọ́nì sọ̀rọ̀ nípa rẹ̀. Onírúurú nǹkan táwa èèyàn máa ń ṣe ló mẹ́nu kan. (Oníwàásù 3:1-8, 10) Ọlọ́run fáwa èèyàn lómìnira láti pinnu ohun tá a fẹ́ ṣe àtìgbà tá a fẹ́ ṣe é. (Diutarónómì 30:19, 20; Jóṣúà 24:15) Sólómọ́nì sọ pé ìgbà téèyàn bá ṣe ohun tí Ọlọ́run fẹ́, to sì fara mọ́ “àkókò” tí Ọlọ́run yàn láti ṣe àwọn nǹkan ló máa tó gbádùn iṣẹ́ àṣekára ẹ̀. Sólómọ́nì sì pe èyí ní “ẹ̀bùn Ọlọ́run.”—Oníwàásù 3:1, 12, 13.

Ka Oníwàásù orí 3 nínú Bíbélì Mímọ́ ti Ìtumọ̀ Ayé Tuntun ẹ̀dà tó wà fún ìkẹ́kọ̀ọ́ lédè Gẹ̀ẹ́sì. Bíbélì yìí rọrùn láti kà, ó sì ní àwọn àtẹ́tísí, àlàyé ọ̀rọ̀ inú Bíbélì, atọ́ka etí ìwé, àwòrán, fídíò àti àwòrán ilẹ̀.

Wo fídíò yìí kó o lè mọ ohun tó wà nínú ìwé Oníwàásù.

    Yorùbá Publications (1987-2025)
    Jáde
    Wọlé
    • Yorùbá
    • Fi Ráńṣẹ́
    • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
    • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
    • Àdéhùn Nípa Lílò
    • Òfin
    • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
    • JW.ORG
    • Wọlé
    Fi Ráńṣẹ́