Wednesday, October 8
Mi ò ní fi ọ́ sílẹ̀ láé.—Héb. 13:5.
Ìgbìmọ̀ Olùdarí fúnra wọn máa ń dá àwọn arákùnrin tó ń ràn wọ́n lọ́wọ́ lẹ́kọ̀ọ́, àwọn arákùnrin yìí sì wà nínú onírúurú ìgbìmọ̀ tí Ìgbìmọ̀ Olùdarí ń lò. Kódà ní báyìí, àwọn arákùnrin yìí ń fi òótọ́ inú bójú tó ọ̀pọ̀ ojúṣe nínú ètò Ọlọ́run. Ìdálẹ́kọ̀ọ́ tí àwọn olùrànlọ́wọ́ Ìgbìmọ̀ Olùdarí ti gbà yìí ti múra wọn sílẹ̀ láti máa bójú tó àwọn àgùntàn Kristi nìṣó. Nígbà tí èyí tó kẹ́yìn lára àwọn ẹni àmì òróró bá ti lọ sọ́run ní apá ìparí ìpọ́njú ńlá, àwa èèyàn Jèhófà á ṣì máa bá ìjọsìn tòótọ́ lọ láyé. Torí pé Jésù ló ń darí wa, àwa èèyàn Ọlọ́run á ṣì máa sìn ín nìṣó, a ò ní pàdánù ohunkóhun. Òótọ́ ni pé nígbà yẹn, Gọ́ọ̀gù ti ilẹ̀ Mágọ́gù, ìyẹn àgbájọ àwọn orílẹ̀-èdè á ti gbéjà kò wá torí pé wọ́n kórìíra wa. (Ìsík. 38:18-20) Àmọ́ àkókò tí wọ́n fi máa gbéjà kò wá ò ní pẹ́, kò sì ní dí àwa èèyàn Jèhófà lọ́wọ́ láti máa jọ́sìn ẹ̀. Ó dájú pé ó máa gbà wá sílẹ̀! Nínú ìran kan, àpọ́sítélì Jòhánù rí “ogunlọ́gọ̀ èèyàn” tó jẹ́ ara àgùntàn mìíràn ti Kristi. Áńgẹ́lì kan sọ fún Jòhánù pé “ogunlọ́gọ̀ èèyàn” yìí wá “látinú ìpọ́njú ńlá.” (Ìfi. 7:9, 14) Torí náà, ó dá wọn lójú pé Jèhófà máa gbà wọ́n là! w24.02 5-6 ¶13-14
Thursday, October 9
Ẹ má ṣe pa iná ẹ̀mí.—1 Tẹs. 5:19.
Kí ló yẹ ká ṣe kí Ọlọ́run lè fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀? Ó yẹ ká máa gbàdúrà pé kó fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, ká máa ka Bíbélì Ọ̀rọ̀ rẹ̀, ká sì wà nínú ètò rẹ̀ tí ẹ̀mí mímọ́ ń darí. Tá a bá ń ṣe àwọn nǹkan yìí, a máa ní “èso ti ẹ̀mí.” (Gál. 5:22, 23) Àwọn tí ọkàn wọn mọ́ àtàwọn tí ìwà wọn mọ́ nìkan ni Ọlọ́run máa ń fún ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀. Tá a bá ń ro èròkerò, tá a sì ṣe ohun tá à ń rò, Ọlọ́run ò ní fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀ mọ́. (1 Tẹs. 4:7, 8) Tá a bá fẹ́ kí Ọlọ́run máa fún wa ní ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀, kò tún yẹ ká “kó àwọn ọ̀rọ̀ àsọtẹ́lẹ̀ dà nù.” (1 Tẹs. 5:20) “Àsọtẹ́lẹ̀” tí ẹsẹ Bíbélì yìí ń sọ nípa ẹ̀ ni àwọn ọ̀rọ̀ tí Jèhófà máa ń bá wa sọ nípasẹ̀ ẹ̀mí mímọ́ ẹ̀. Lára àwọn ọ̀rọ̀ náà ni ọjọ́ Jèhófà tí ò ní pẹ́ dé àti bí àkókò tá a wà yìí ti ṣe pàtàkì tó. Kò yẹ ká máa rò pé ọjọ́ Jèhófà tàbí Amágẹ́dọ́nì ò ní dé lákòókò wa yìí. Kàkà bẹ́ẹ̀, ṣe ló yẹ ká máa ṣe àwọn ohun tó fi hàn pé ọjọ́ náà ò ní pẹ́ dé, ká máa hùwà tó dáa, ká sì máa ṣe “iṣẹ́ ìfọkànsin Ọlọ́run.”—2 Pét. 3:11, 12. w23.06 12-13 ¶13-14
Friday, October 10
Ìbẹ̀rù Jèhófà ni ìbẹ̀rẹ̀ ọgbọ́n.—Òwe 9:10.
Kí ló yẹ ká ṣe tí àwòrán ìṣekúṣe bá ṣàdédé jáde lórí fóònù tàbí kọ̀ǹpútà wa? Ṣe ló yẹ ká gbé ojú wa kúrò lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀. Ohun tó máa jẹ́ ká ṣe bẹ́ẹ̀ ni tá a bá rántí pé àjọṣe wa pẹ̀lú Jèhófà ló ṣeyebíye jù lọ. Kódà, àwọn àwòrán kan wà tí kì í ṣe àwòrán ìṣekúṣe tó lè mú ká máa ro èròkerò. Kí nìdí tí ò fi yẹ ká máa wo irú àwọn àwòrán bẹ́ẹ̀? Ìdí ni pé ó lè mú ká ṣàgbèrè nínú ọkàn wa, a ò sì ní fẹ́ ṣe bẹ́ẹ̀. (Mát. 5:28, 29) Alàgbà kan tó ń jẹ́ David lórílẹ̀-èdè Thailand sọ pé: “Mo máa ń bi ara mi pé, ‘Tí àwòrán kan kì í bá tiẹ̀ ṣe àwòrán ìṣekúṣe, ṣé inú Jèhófà máa dùn sí mi tí mo bá ń wò ó?’ Ìbéèrè tí mo máa ń bi ara mi yìí kì í jẹ́ kí n wo irú àwọn àwòrán bẹ́ẹ̀.” Tá a bá ń bẹ̀rù Jèhófà tọkàntọkàn, a ò ní ṣe ohun tí ò fẹ́. Ìbẹ̀rù Ọlọ́run ni “ìbẹ̀rẹ̀” tàbí ìpìlẹ̀ “ọgbọ́n.” w23.06 23 ¶12-13