ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Yorùbá
ọ́
  • ẹ
  • ọ
  • ṣ
  • ń
  • ẹ́
  • ẹ̀
  • ọ́
  • ọ̀
  • BÍBÉLÌ
  • ÌTẸ̀JÁDE
  • ÌPÀDÉ
Yorùbá Publications (1987-2025)
Jáde
Wọlé
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍNTÁNẸ́Ẹ̀TÌ ti Watchtower
ÀKÁ ÌWÉ ORÍ ÍŃTÁNẸ́Ẹ̀TÌ
ti Watchtower
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
Ìfilọ̀
Èdè tuntun tó wà: Dendi
  • Òní

Monday, July 28

Ẹni tó wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú yín tóbi ju ẹni tó wà ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ayé.—1 Jòh. 4:4.

Tẹ́rù bá ń bà ẹ́, máa ronú nípa àwọn nǹkan tí Jèhófà máa ṣe lọ́jọ́ iwájú nígbà tí Sátánì ò ní sí mọ́. Àwòrán tó wà nínú ìtòlẹ́sẹẹsẹ àpéjọ agbègbè ọdún 2014 jẹ́ ká rí bí bàbá kan ṣe ń jíròrò ohun tó wà nínú 2 Tímótì 3:​1-5 pẹ̀lú ìdílé ẹ̀, ó sì sọ ọ́ bíi pé àsọtẹ́lẹ̀ ohun tó máa ṣẹlẹ̀ nínú Párádísè ló ń sọ. Ó sọ pé: “Inú ayé tuntun ni inú wa ti máa dùn jù. Àwọn èèyàn máa nífẹ̀ẹ́ ara wọn, wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ òtítọ́, wọ́n máa mọ̀wọ̀n ara wọn, wọ́n máa nírẹ̀lẹ̀, wọ́n á máa yin Ọlọ́run, àwọn ọmọ á máa gbọ́ràn sí òbí wọn lẹ́nu, wọ́n á máa moore, wọ́n á jẹ́ olóòótọ́, wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ ìdílé wọn gan-an, àwọn èèyàn á máa gbọ́ ara wọn yé, wọ́n á máa sọ̀rọ̀ tó dáa nípa àwọn ẹlòmíì, wọ́n á ní ìkóra-ẹni-níjàánu, wọ́n máa níwà tútù, wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ ohun rere, wọ́n á ṣeé gbẹ́kẹ̀ lé, wọ́n á máa fòye báni lò, wọn ò ní máa gbéra ga, wọ́n máa nífẹ̀ẹ́ Ọlọ́run dípò ìgbádùn, wọ́n á máa fọkàn sin Ọlọ́run, irú àwọn èèyàn yìí ni kó o máa bá ṣọ̀rẹ́.” Ṣé ìwọ àti ìdílé ẹ tàbí àwọn ará míì jọ máa ń sọ bí nǹkan ṣe máa rí nínú ayé tuntun? w24.01 6 ¶13-14

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Tuesday, July 29

Mo ti tẹ́wọ́ gbà ọ́.—Lúùkù 3:22.

Ó dájú pé ọkàn wa balẹ̀ gan-an bá a ṣe mọ̀ pé inú Jèhófà ń dùn sí gbogbo àwa èèyàn ẹ̀. Bíbélì sọ pé: “Inú Jèhófà ń dùn sí àwọn èèyàn rẹ̀.” (Sm. 149:4) Àmọ́ nígbà míì, àwọn kan máa ń rẹ̀wẹ̀sì, wọ́n sì máa ń bi ara wọn pé, ‘Ṣé inú Jèhófà ń dùn sí mi ṣá?’ Ọ̀pọ̀ àwọn olóòótọ́ ìránṣẹ́ Jèhófà tí Bíbélì sọ̀rọ̀ wọn náà rẹ̀wẹ̀sì láwọn ìgbà kan, ó sì ṣòro fún wọn láti gbà pé inú Jèhófà ń dùn sí wọn. (1 Sám. 1:​6-10; Jóòbù 29:​2, 4; Sm. 51:11) Bíbélì jẹ́ ká mọ̀ pé inú Jèhófà máa ń dùn sí àwa èèyàn aláìpé. Àmọ́ kí la gbọ́dọ̀ ṣe kínú ẹ̀ tó lè dùn sí wa? A gbọ́dọ̀ nígbàgbọ́ nínú Jésù Kristi, ká sì ṣèrìbọmi. (Jòh. 3:16) Ìyẹn lá fi hàn pé a ti ronú pìwà dà àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, a sì ti ṣèlérí fún Ọlọ́run pé ìfẹ́ rẹ̀ la máa ṣe. (Ìṣe 2:38; 3:19) Inú Jèhófà máa ń dùn gan-an tá a bá ṣe àwọn nǹkan yìí ká lè ní àjọṣe tó dáa pẹ̀lú ẹ̀. Tá a bá ń ṣe gbogbo ohun tá a lè ṣe láti mú ẹ̀jẹ́ ìyàsímímọ́ wa ṣẹ, inú Jèhófà máa dùn sí wa, á sì kà wá sí ọ̀rẹ́ ẹ̀ tímọ́tímọ́.—Sm. 25:14. w24.03 26 ¶1-2

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025

Wednesday, July 30

A ò lè ṣàì sọ ohun tí a ti rí tí a sì ti gbọ́.—Ìṣe 4:20.

Ó yẹ káwa náà máa wàásù bíi tàwọn ọmọ ẹ̀yìn Jésù tí ìjọba bá tiẹ̀ sọ pé ká má wàásù mọ́. Ó yẹ kó dá àwa náà lójú pé Jèhófà máa ràn wá lọ́wọ́ lẹ́nu iṣẹ́ ìwàásù wa. Torí náà, gbàdúrà sí Jèhófà pé kó fún ẹ nígboyà àti ọgbọ́n. Bẹ̀ ẹ́ pé kó ràn ẹ́ lọ́wọ́ láti fara da ìṣòro ẹ. Ọ̀pọ̀ lára àwa ìránṣẹ́ Jèhófà ló ń fara da àìsàn, ìdààmú ọkàn, ikú èèyàn wa kan, ìṣòro ìdílé tó le gan-an, inúnibíni àtàwọn ìṣòro míì. Àwọn nǹkan bí àjàkálẹ̀ àrùn àti ogun sì ti mú káwọn nǹkan yìí túbọ̀ nira fáwọn ará wa. Torí náà, sọ gbogbo bó ṣe ń ṣe ẹ́ fún Jèhófà. Sọ ìṣòro tó o ní fún Jèhófà bó o ṣe máa sọ fún ọ̀rẹ́ ẹ tímọ́tímọ́. Tó o bá ṣe bẹ́ẹ̀, mọ̀ dájú pé Jèhófà máa “gbé ìgbésẹ̀ nítorí rẹ.” (Sm. 37:​3, 5) Tá a bá tẹra mọ́ àdúrà, ó máa jẹ́ ká “fara da ìpọ́njú.” (Róòmù 12:12) Jèhófà mọ ohun táwa ìránṣẹ́ ẹ̀ ń bá yí, ‘ó sì máa ń gbọ́ igbe wa tá a bá ní kó ràn wá lọ́wọ́.’—Sm. 145:​18, 19. w23.05 5-6 ¶12-15

Máa Ṣàyẹ̀wò Ìwé Mímọ́ Lójoojúmọ́—2025
Ẹ Káàbọ̀.
Ìkànnì yìí wà fún ṣíṣe ìwádìí látinú àwọn ìwé tí àwa Ẹlẹ́rìí Jèhófà ṣe ní oríṣiríṣi èdè.
Bí o bá fẹ́ wa ìwé jáde, jọ̀wọ́ lọ sí jw.org.
  • Yorùbá
  • Fi Ráńṣẹ́
  • Èyí tí mo fẹ́ràn jù
  • Copyright © 2025 Watch Tower Bible and Tract Society of Pennsylvania
  • Àdéhùn Nípa Lílò
  • Òfin
  • Ètò Nípa Ìsọfúnni Rẹ
  • JW.ORG
  • Wọlé
Fi Ráńṣẹ́