Saturday, August 2
Máa tẹrí ba fún àwọn aláṣẹ onípò gíga.—Róòmù 13:1.
A lè kẹ́kọ̀ọ́ lára Jósẹ́fù àti Màríà tí wọ́n ṣègbọràn sí ìjọba bó tiẹ̀ jẹ́ pé kò rọrùn. (Lúùkù 2:1-6) Nígbà tí oyún inú Màríà pé nǹkan bí oṣù mẹ́sàn-án, ìjọba ṣòfin kan tí ò rọrùn fún wọn láti pa mọ́. Augustus tó ń ṣàkóso ìjọba Róòmù pàṣẹ pé kí gbogbo èèyàn lọ forúkọ sílẹ̀ nílùú ìbílẹ̀ wọn. Torí náà, Jósẹ́fù àti Màríà rìnrìn àjò gba òkè gbágungbàgun lọ sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù, ìrìn àjò náà sì tó nǹkan bí àádọ́jọ kìlómítà (150). Ó dájú pé ìrìn àjò yẹn ò lè rọrùn, pàápàá fún Màríà. Ẹ̀rù lè máa ba àwọn méjèèjì torí wọn ò fẹ́ kí nǹkan kan ṣẹlẹ̀ sí Màríà àti oyún inú ẹ̀. Wọ́n lè máa ṣàníyàn nípa ohun tó lè ṣẹlẹ̀ tí Màríà bá bẹ̀rẹ̀ sí í rọbí. Ìdí sì ni pé oyún Mèsáyà tí gbogbo èèyàn ń dúró dè ló wà nínú ẹ̀. Ṣéyẹn á wá mú kí wọ́n má ṣègbọràn síjọba? Jósẹ́fù àti Màríà ò jẹ́ káwọn nǹkan yẹn dí wọn lọ́wọ́ láti ṣègbọràn sí òfin yẹn. Inú Jèhófà dùn sí wọn, ó sì jẹ́ kí ìrìn àjò wọn yọrí sí rere. Màríà dé sí Bẹ́tílẹ́hẹ́mù láyọ̀ àti àlàáfíà, ó bí ọmọ náà wẹ́rẹ́, ó sì ṣe ohun tó mú kí àsọtẹ́lẹ̀ Bíbélì ṣẹ!—Míkà 5:2. w23.10 8 ¶9; 9 ¶11-12
Sunday, August 3
Ká máa gba ara wa níyànjú.—Héb. 10:25.
Kí lo lè ṣe tẹ́rù bá ń bà ẹ́ láti dáhùn nípàdé? Múra ìdáhùn ẹ dáadáa. (Òwe 21:5) Bó o bá ṣe múra ohun tẹ́ ẹ fẹ́ kọ́ dáadáa, bẹ́ẹ̀ lọkàn ẹ máa balẹ̀ láti dáhùn. Bákan náà, jẹ́ kí ìdáhùn ẹ ṣe ṣókí. (Òwe 15:23; 17:27) Tí ìdáhùn ẹ bá ṣe ṣókí, ẹ̀rù ò ní bà ẹ́. Tó o bá dáhùn ṣókí lọ́rọ̀ ara ẹ, ìyẹn fi hàn pé o múra sílẹ̀ dáadáa àti pé ohun tá à ń kọ́ yé ẹ. Ká sọ pé o tẹ̀ lé gbogbo àwọn àbá tá a sọ yìí, àmọ́ tẹ́rù ṣì ń bà ẹ́ láti dáhùn ju ẹ̀ẹ̀kan lọ ńkọ́? Mọ̀ dájú pé Jèhófà mọyì bó o ṣe ń ṣe gbogbo ohun tó o lè ṣe láti dáhùn. (Lúùkù 21:1-4) Rántí pé Jèhófà ò retí pé kó o ṣe ju agbára ẹ lọ. (Fílí. 4:5) Ó yẹ kíwọ fúnra ẹ mọ ohun tí agbára ẹ gbé, kó o mọ bó o ṣe máa ṣe é, kó o sì gbàdúrà sí Jèhófà kẹ́rù má bà ẹ́ mọ́. Ohun tó o lè fi bẹ̀rẹ̀ ni pé kó o dáhùn lẹ́ẹ̀kan nípàdé, kó o sì jẹ́ kó ṣe ṣókí. w23.04 21 ¶6-8
Monday, August 4
Gbé àwo ìgbàyà wọ̀, kí o sì dé akoto.—1 Tẹs. 5:8.
Àpọ́sítélì Pọ́ọ̀lù fi àwa Kristẹni wé àwọn sójà tó máa ń wà lójúfò, tí wọ́n sì máa ń múra sílẹ̀ de ogun. Àwọn èèyàn gbà pé ó yẹ kí sójà kan múra sílẹ̀ láti jà torí ìgbàkigbà ni ogun lè dé. Bọ́rọ̀ tiwa náà ṣe rí nìyẹn. Tá a bá fẹ́ fi hàn pé lóòótọ́ là ń múra sílẹ̀ de ọjọ́ Jèhófà, ó yẹ ká gbé àwo ìgbàyà wọ̀, ìyẹn ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́, ká sì dé akoto, ìyẹn ìrètí tá a ní. Àwo ìgbàyà máa ń dáàbò bo àyà sójà kan. Bẹ́ẹ̀ náà ni ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ ṣe máa ń dáàbò bo ọkàn ìṣàpẹẹrẹ wa. Àwọn ànímọ́ yìí máa ń jẹ́ ká sin Jèhófà nìṣó, ká sì máa tẹ̀ lé àpẹẹrẹ Jésù. Ìgbàgbọ́ tá a ní máa ń jẹ́ kó dá wa lójú pé Jèhófà máa san èrè fún wa tá a bá sìn ín tọkàntọkàn. (Héb. 11:6) Ó máa ń jẹ́ ká jẹ́ olóòótọ́ sí Jésù Aṣáájú wa kódà bá a tiẹ̀ ń fara da ọ̀pọ̀ ìṣòro. A lè mú kí ìgbàgbọ́ wa túbọ̀ lágbára tá a bá ń kẹ́kọ̀ọ́ nípa àpẹẹrẹ àwọn tó jẹ́ olóòótọ́ sí Jèhófà lásìkò wa yìí bó tiẹ̀ jẹ́ pé wọ́n ń fara da inúnibíni tàbí ìṣòro àìlówó lọ́wọ́. Yàtọ̀ síyẹn, tá ò bá fẹ́ kó sínú ìdẹkùn kíkó ohun ìní jọ, ó yẹ ká máa fara wé àwọn tí wọ́n jẹ́ kí ohun ìní díẹ̀ tẹ́ wọn lọ́rùn kí wọ́n lè fi Ìjọba Ọlọ́run sípò àkọ́kọ́. w23.06 10 ¶8-9